31 Térà wá mú Ábúrámù ọmọ rẹ̀ àti Lọ́ọ̀tì tó jẹ́ ọmọ ọmọ rẹ̀,+ ọmọ Háránì, ó sì mú Sáráì, ìyàwó Ábúrámù ọmọ rẹ̀, wọ́n sì tẹ̀ lé e nígbà tó kúrò ní Úrì ti àwọn ará Kálídíà láti lọ sí ilẹ̀ Kénáánì.+ Nígbà tó yá, wọ́n dé Háránì,+ wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ibẹ̀.