ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Léfítíkù 19:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 “‘Ẹ ò gbọ́dọ̀ jẹ ohunkóhun tòun ti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.+

      “‘Ẹ ò gbọ́dọ̀ woṣẹ́, ẹ ò sì gbọ́dọ̀ pidán.+

  • Léfítíkù 20:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 “‘Ní ti ẹni tó bá tọ àwọn abẹ́mìílò+ lọ àti àwọn woṣẹ́woṣẹ́+ kó lè bá wọn ṣe àgbèrè ẹ̀sìn, ó dájú pé màá bínú sí onítọ̀hún,* màá sì pa á, kí n lè mú un kúrò láàárín àwọn èèyàn rẹ̀.+

  • Diutarónómì 18:10-12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Ẹnì kankan láàárín yín ò gbọ́dọ̀ sun ọmọkùnrin rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin rẹ̀ nínú iná,+ kò gbọ́dọ̀ woṣẹ́,+ kò gbọ́dọ̀ pidán,+ kò gbọ́dọ̀ wá àmì ohun tó fẹ́ ṣẹlẹ̀,+ kò gbọ́dọ̀ di oṣó,+ 11 kò gbọ́dọ̀ fi èèdì di àwọn ẹlòmíì, kò gbọ́dọ̀ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ abẹ́mìílò+ tàbí woṣẹ́woṣẹ́,+ kò sì gbọ́dọ̀ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ òkú.+ 12 Torí Jèhófà kórìíra ẹnikẹ́ni tó bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, torí àwọn ohun ìríra yìí sì ni Jèhófà Ọlọ́run yín ṣe máa lé wọn kúrò níwájú yín.

  • 1 Sámúẹ́lì 28:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Lákòókò yìí, Sámúẹ́lì ti kú, gbogbo Ísírẹ́lì ti ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, wọ́n sì ti sin ín sí Rámà ìlú rẹ̀.+ Sọ́ọ̀lù sì ti mú àwọn abẹ́mìílò àti àwọn woṣẹ́woṣẹ́ kúrò ní ilẹ̀ náà.+

  • Gálátíà 5:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 ìbọ̀rìṣà, ìbẹ́mìílò,*+ ìkórìíra, wàhálà, owú, inú fùfù, awuyewuye, ìpínyà, ẹ̀ya ìsìn,

  • Ìfihàn 22:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Ìta ni àwọn ajá* wà àti àwọn tó ń bá ẹ̀mí lò àti àwọn oníṣekúṣe* àti àwọn apààyàn àti àwọn abọ̀rìṣà àti gbogbo àwọn tó fẹ́ràn irọ́, tí wọ́n sì ń parọ́.’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́