2 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Sọ fún Áárónì ẹ̀gbọ́n rẹ pé kó má kàn wá sínú ibi mímọ́+ tó wà lẹ́yìn aṣọ ìdábùú+ nígbàkigbà, níwájú ìbòrí Àpótí, kó má bàa kú,+ torí màá fara hàn nínú ìkùukùu*+ lórí ìbòrí+ náà.
19 Torí náà, ẹ̀yin ará, nígbà tó jẹ́ pé a ní ìgboyà* láti wá sí ọ̀nà tó wọnú ibi mímọ́+ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Jésù, 20 èyí tó ṣí sílẹ̀* fún wa bí ọ̀nà tuntun, tó sì jẹ́ ọ̀nà ìyè tó la aṣọ ìdábùú kọjá,+ ìyẹn ẹran ara rẹ̀,