-
Léfítíkù 20:10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 “‘Tí ọkùnrin kan bá bá ìyàwó ọkùnrin míì ṣe àgbèrè: Ẹ gbọ́dọ̀ pa ẹni tó bá ìyàwó ẹnì kejì rẹ̀ ṣe àgbèrè, ọkùnrin alágbèrè àti obìnrin alágbèrè náà.+
-
-
Diutarónómì 22:22Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 “Tí ẹ bá rí ọkùnrin kan tó bá obìnrin tó jẹ́ ìyàwó ẹlòmíì sùn, ṣe ni kí ẹ pa àwọn méjèèjì, ọkùnrin tó bá obìnrin náà sùn pẹ̀lú obìnrin yẹn.+ Kí ẹ mú ohun tó burú kúrò ní Ísírẹ́lì.
-
-
1 Kọ́ríńtì 6:9, 10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Àbí ẹ ò mọ̀ pé àwọn aláìṣòdodo kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run ni?+ Ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n ṣì yín lọ́nà.* Àwọn oníṣekúṣe,*+ àwọn abọ̀rìṣà,+ àwọn alágbèrè,+ àwọn ọkùnrin tó ń jẹ́ kí ọkùnrin bá wọn lò pọ̀,+ àwọn abẹ́yà-kan-náà-lòpọ̀,*+ 10 àwọn olè, àwọn olójúkòkòrò,+ àwọn ọ̀mùtípara,+ àwọn pẹ̀gànpẹ̀gàn* àti àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run.+
-