8 Jèhófà tún sọ fún Áárónì pé: “Èmi fúnra mi fi gbogbo ọrẹ tí wọ́n bá ṣe fún mi+ sí ìkáwọ́ rẹ. Mo ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ lára gbogbo ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá fi ṣe ọrẹ, kó jẹ́ ìpín+ yín títí lọ.
30 Èyí tó dáa jù nínú gbogbo àkọ́so èso àti onírúurú ọrẹ tí ẹ bá mú wá yóò di ti àwọn àlùfáà.+ Kí ẹ fún àlùfáà ní àkọ́so ọkà yín tí ẹ ò lọ̀ kúnná.+ Èyí máa mú kí ìbùkún wà lórí ilé yín.+