ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Léfítíkù 16:34
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 34 Èyí máa jẹ́ àṣẹ tí ẹ ó máa pa mọ́ títí lọ,+ láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lẹ́ẹ̀kan lọ́dún+ torí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”

      Torí náà, ó ṣe ohun tí Jèhófà pa láṣẹ fún Mósè gẹ́lẹ́.

  • Hébérù 9:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Kì í ṣe ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ àti ti àwọn akọ ọmọ màlúù ló gbé wọnú ibi mímọ́, àmọ́ ẹ̀jẹ̀ òun fúnra rẹ̀ ni,+ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé, ó sì gba ìtúsílẹ̀* àìnípẹ̀kun fún wa.+

  • Hébérù 9:24-26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Torí Kristi ò wọnú ibi mímọ́ tí wọ́n fi ọwọ́ ṣe,+ tó jẹ́ àpẹẹrẹ ohun gidi,+ àmọ́ ọ̀run gangan ló wọ̀ lọ,+ tó fi jẹ́ pé ó ń fara hàn báyìí níwájú* Ọlọ́run nítorí wa.+ 25 Kò ṣe èyí láti máa fi ara rẹ̀ rúbọ léraléra bí ìgbà tí àlùfáà àgbà máa ń wọ ibi mímọ́ lọ́dọọdún+ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ tí kì í ṣe tiẹ̀. 26 Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ì bá máa jìyà léraléra látìgbà ìpìlẹ̀ ayé. Àmọ́ ní báyìí, ó ti fi ara rẹ̀ hàn kedere ní ìparí àwọn ètò àwọn nǹkan,* lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé, ó fi ara rẹ̀ rúbọ kó lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò.+

  • Hébérù 10:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Nípasẹ̀ “ìfẹ́” yìí,+ a ti fi ara Jésù Kristi tó fi rúbọ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé sọ wá di mímọ́.+

  • 1 Jòhánù 2:1, 2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké, mò ń kọ àwọn nǹkan yìí sí yín kí ẹ má bàa dẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀, tí ẹnikẹ́ni bá dẹ́ṣẹ̀, a ní olùrànlọ́wọ́* lọ́dọ̀ Baba, Jésù Kristi,+ ẹni tó jẹ́ olódodo.+ 2 Òun sì ni ẹbọ ìpẹ̀tù*+ fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa,+ síbẹ̀ kì í ṣe fún ẹ̀ṣẹ̀ tiwa nìkan, àmọ́ fún gbogbo ayé pẹ̀lú.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́