-
Nọ́ńbà 28:11-13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 “‘Ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù kọ̀ọ̀kan,* kí ẹ mú akọ ọmọ màlúù méjì, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́ àgùntàn méje tí ara wọn dá ṣáṣá tí ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ọlọ́dún kan+ wá láti fi rú ẹbọ sísun sí Jèhófà, 12 pẹ̀lú ìyẹ̀fun kíkúnná tó jẹ́ ìdá mẹ́ta nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n tí wọ́n pò mọ́ òróró láti fi ṣe ọrẹ ọkà + fún akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti ìyẹ̀fun kíkúnná tó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n tí wọ́n pò mọ́ òróró láti fi ṣe ọrẹ ọkà fún àgbò+ náà, 13 pẹ̀lú ìyẹ̀fun kíkúnná tó jẹ́ ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n tí wọ́n pò mọ́ òróró láti fi ṣe ọrẹ ọkà fún akọ ọ̀dọ́ àgùntàn kọ̀ọ̀kan, láti fi rú ẹbọ sísun tó ń mú òórùn dídùn*+ jáde, ọrẹ àfinásun sí Jèhófà.
-