ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nọ́ńbà 26:63, 64
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 63 Èyí ni àwọn tí Mósè àti àlùfáà Élíásárì forúkọ wọn sílẹ̀ nígbà tí wọ́n forúkọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀ ní aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Móábù, nítòsí Jọ́dánì ní Jẹ́ríkò. 64 Àmọ́ ìkankan nínú wọn kò sí lára àwọn tí Mósè àti àlùfáà Áárónì forúkọ wọn sílẹ̀ nígbà tí wọ́n ka iye àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní aginjù Sínáì.+

  • Nọ́ńbà 32:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 ‘Àwọn ọkùnrin tó kúrò ní Íjíbítì, láti ẹni ogún (20) ọdún sókè kò ní rí ilẹ̀  + tí mo búra pé màá fún Ábúráhámù, Ísákì àti Jékọ́bù,+ torí pé wọn ò fi gbogbo ọkàn wọn tọ̀ mí lẹ́yìn,

  • Diutarónómì 1:35
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 35 ‘Ìkankan nínú àwọn èèyàn yìí tí wọ́n wà lára ìran búburú yìí kò ní rí ilẹ̀ dáradára tí mo búra pé màá fún àwọn bàbá yín,+

  • Sáàmù 95:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Torí náà, mo búra nínú ìbínú mi pé:

      “Wọn ò ní wọnú ìsinmi mi.”+

  • Sáàmù 106:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 Torí náà, ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti búra nípa wọn

      Pé òun máa mú kí wọ́n ṣubú ní aginjù;+

  • Hébérù 3:18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 Àwọn wo ló sì búra fún pé wọn ò ní wọnú ìsinmi òun? Ṣebí àwọn tó ṣàìgbọràn ni?

  • Hébérù 4:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Torí àwa tí a ní ìgbàgbọ́ wọnú ìsinmi náà, bó ṣe sọ pé: “Torí náà, mo búra nínú ìbínú mi pé, ‘Wọn ò ní wọnú ìsinmi mi,’”+ bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn iṣẹ́ rẹ̀ ti parí látìgbà ìpìlẹ̀ ayé.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́