ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 34:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Jèhófà ń kọjá níwájú rẹ̀, ó sì ń kéde pé: “Jèhófà, Jèhófà, Ọlọ́run aláàánú,+ tó ń gba tẹni rò,*+ tí kì í tètè bínú,+ tí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀*+ àti òtítọ́*+ rẹ̀ sì pọ̀ gidigidi,

  • Diutarónómì 30:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 nígbà náà, Jèhófà Ọlọ́run rẹ máa mú àwọn èèyàn rẹ tí wọ́n kó lẹ́rú+ pa dà wá, ó máa ṣàánú+ rẹ, ó sì máa kó ọ jọ látọ̀dọ̀ gbogbo èèyàn tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ tú ọ+ ká sí.

  • 2 Kíróníkà 30:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Torí ìgbà tí ẹ bá pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà ni àwọn arákùnrin yín àti àwọn ọmọ yín máa rí àánú gbà látọ̀dọ̀ àwọn tó mú wọn lẹ́rú,+ wọ́n á sì jẹ́ kí wọ́n pa dà sí ilẹ̀ yìí,+ nítorí Jèhófà Ọlọ́run yín jẹ́ ẹni tó ń gba tẹni rò* àti aláàánú,+ kò sì ní yí ojú rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ yín tí ẹ bá pa dà sọ́dọ̀ rẹ̀.”+

  • Nehemáyà 9:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 Nínú àánú ńlá rẹ, o ò pa wọ́n run,+ o ò sì fi wọ́n sílẹ̀, nítorí Ọlọ́run tó ń gba tẹni rò* àti aláàánú ni ọ́.+

  • Àìsáyà 54:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 “Torí mo pa ọ́ tì fún ìgbà díẹ̀,

      Àmọ́ màá ṣàánú rẹ gidigidi, màá sì kó ọ jọ pa dà.+

  • Àìsáyà 55:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 Kí èèyàn burúkú fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀,+

      Kí ẹni ibi sì yí èrò rẹ̀ pa dà;

      Kó pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà, ẹni tó máa ṣàánú rẹ̀,+

      Sọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, torí ó máa dárí jini fàlàlà.*+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́