-
Diutarónómì 8:7-9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Torí ilẹ̀ dáradára ni Jèhófà Ọlọ́run rẹ ń mú ọ lọ,+ ilẹ̀ tí omi ti ń ṣàn,* tí omi ti ń sun jáde, tí omi sì ti ń tú jáde* ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ní agbègbè olókè, 8 ilẹ̀ tí àlìkámà* àti ọkà bálì kún inú rẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi àjàrà, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pómégíránétì,+ ilẹ̀ tí òróró ólífì àti oyin kún inú rẹ̀,+ 9 ilẹ̀ tí oúnjẹ ò ti ní wọ́n ọ, tó ò sì ní ṣaláìní ohunkóhun, ilẹ̀ tí irin wà nínú àwọn òkúta rẹ̀, tí wàá sì máa wa bàbà látinú àwọn òkè rẹ̀.
-
-
Jeremáyà 14:22Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Ǹjẹ́ ìkankan lára àwọn òrìṣà lásánlàsàn tí àwọn orílẹ̀-èdè ń bọ lè rọ òjò,
Àbí ṣé ọ̀run fúnra rẹ̀ pàápàá lè dá rọ ọ̀wààrà òjò?
Ìwọ nìkan lo lè ṣe é, Jèhófà Ọlọ́run wa.+
A sì ní ìrètí nínú rẹ,
Nítorí ìwọ nìkan ló ń ṣe gbogbo nǹkan yìí.
-