-
2 Kíróníkà 25:1-4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
25 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni Amasááyà nígbà tó jọba, ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n (29) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Jèhóádánì láti Jerúsálẹ́mù.+ 2 Ó ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Jèhófà, àmọ́ kì í ṣe pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀. 3 Nígbà tí ìjọba rẹ̀ ti fìdí múlẹ̀ dáadáa, ó pa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n pa bàbá rẹ̀ ọba.+ 4 Àmọ́ kò pa àwọn ọmọ wọn, torí pé ó ṣe ohun tó wà lákọsílẹ̀ nínú Òfin, nínú ìwé Mósè, níbi tí Jèhófà ti pàṣẹ pé: “Àwọn bàbá kò gbọ́dọ̀ kú nítorí àwọn ọmọ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ kò gbọ́dọ̀ kú nítorí àwọn bàbá; kí kálukú kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tirẹ̀.”+
-