6 Ó ṣẹlẹ̀ pé àwọn ọkùnrin kan di aláìmọ́ torí wọ́n fara kan òkú èèyàn,*+ wọn ò wá lè ṣètò ẹbọ Ìrékọjá ní ọjọ́ yẹn. Torí náà, àwọn ọkùnrin náà wá sọ́dọ̀ Mósè àti Áárónì ní ọjọ́ yẹn,+
10 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Tí ẹnikẹ́ni nínú yín tàbí nínú àwọn ìran yín tó ń bọ̀ bá di aláìmọ́ torí pé ó fara kan òkú èèyàn*+ tàbí tí ó rin ìrìn àjò ọ̀nà jíjìn, ẹni náà ṣì gbọ́dọ̀ ṣètò ẹbọ Ìrékọjá fún Jèhófà.