-
Ẹ́sírà 4:1-3Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 Nígbà tí àwọn ọ̀tá Júdà àti Bẹ́ńjámínì + gbọ́ pé àwọn tó dé láti ìgbèkùn+ ń kọ́ tẹ́ńpìlì kan fún Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, 2 ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni wọ́n lọ bá Serubábélì àti àwọn olórí agbo ilé, wọ́n sì sọ fún wọn pé: “Ẹ jẹ́ ká jọ kọ́ ilé yìí; nítorí Ọlọ́run yín làwa náà ń sìn,*+ òun la sì ń rúbọ sí láti ìgbà ayé Esari-hádónì+ ọba Ásíríà tó kó wa wá síbí.”+ 3 Àmọ́, Serubábélì àti Jéṣúà pẹ̀lú ìyókù àwọn olórí agbo ilé ní Ísírẹ́lì sọ fún wọn pé: “Kò sí ohun tó kàn yín nínú kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa,+ àwa nìkan ló máa kọ́ ọ fún Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, gẹ́gẹ́ bí Ọba Kírúsì tó jẹ́ ọba Páṣíà ṣe pàṣẹ fún wa.”+
-