25Síwájú sí i, Dáfídì àti àwọn olórí àwùjọ àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn ya àwọn kan lára àwọn ọmọ Ásáfù, Hémánì àti Jédútúnì+ sọ́tọ̀ láti máa fi háàpù, àwọn ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín+ àti síńbálì*+ sọ tẹ́lẹ̀. Orúkọ àwọn tó ń ṣe iṣẹ́ ìsìn yìí ni,
15 Àwọn akọrin, ìyẹn àwọn ọmọ Ásáfù,+ wà ní àyè wọn gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dáfídì+ àti Ásáfù+ àti Hémánì pẹ̀lú Jédútúnì+ aríran ọba; àwọn aṣọ́bodè sì wà ní ẹnubodè kọ̀ọ̀kan.+ Kò sí ìdí fún wọn láti kúrò lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wọn, nítorí pé àwọn arákùnrin wọn àwọn ọmọ Léfì ti ṣètò nǹkan sílẹ̀ fún wọn.