5 Má bẹ̀rù, torí mo wà pẹ̀lú rẹ.+
Màá mú ọmọ rẹ wá láti ìlà oòrùn,
Màá sì kó ọ jọ láti ìwọ̀ oòrùn.+
6 Màá sọ fún àríwá pé, ‘Dá wọn sílẹ̀!’+
Màá sì sọ fún gúúsù pé, ‘Má ṣe dá wọn dúró.
Mú àwọn ọmọkùnrin mi wá láti ọ̀nà jíjìn àti àwọn ọmọbìnrin mi láti àwọn ìkángun ayé,+
-
Jeremáyà 31:8
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Màá mú wọn pa dà wá láti ilẹ̀ àríwá.+
Màá sì kó wọn jọ láti ibi tó jìnnà jù lọ láyé.+
Àwọn afọ́jú àti àwọn arọ máa wà lára wọn,+
Aboyún àti ẹni tó ń rọbí, gbogbo wọn pa pọ̀.
Bí ìjọ ńlá ni wọ́n máa pa dà sí ibí yìí.+