-
Diutarónómì 17:8, 9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 “Tí ohun kan bá ṣẹlẹ̀ ní ọ̀kan lára àwọn ìlú rẹ, tí ẹjọ́ náà sì ṣòroó dá, bóyá ọ̀rọ̀ nípa ìtàjẹ̀sílẹ̀+ tàbí ẹnì kan fẹ́ gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ tàbí àwọn kan hùwà ipá tàbí àwọn ẹjọ́ míì tó jẹ mọ́ fífa ọ̀rọ̀, kí o gbéra, kí o sì lọ sí ibi tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ yàn.+ 9 Lọ bá àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Léfì àti adájọ́+ tó ń gbẹ́jọ́ nígbà yẹn, kí o ro ẹjọ́ náà fún wọn, wọ́n á sì bá ọ dá a.+
-
-
2 Kíróníkà 19:8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Ní Jerúsálẹ́mù, Jèhóṣáfátì tún yan àwọn kan lára àwọn ọmọ Léfì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn kan lára àwọn olórí agbo ilé Ísírẹ́lì láti máa ṣe onídàájọ́ fún Jèhófà àti láti máa yanjú àwọn ẹjọ́ fún àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù.+
-