7 “Ṣáà rí i pé o jẹ́ onígboyà àti alágbára gidigidi, kí o sì rí i pé ò ń tẹ̀ lé gbogbo Òfin tí Mósè ìránṣẹ́ mi pa láṣẹ fún ọ. Má yà kúrò nínú rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì,+ kí o lè máa hùwà ọgbọ́n níbikíbi tí o bá lọ.+
5 Torí náà, tí ẹnikẹ́ni nínú yín ò bá ní ọgbọ́n, kó máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run,+ ó sì máa fún un,+ torí ó lawọ́ sí gbogbo èèyàn, kì í sì í pẹ̀gàn*+ tó bá ń fúnni.