Sáàmù 51:1 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 51 Ọlọ́run, ṣojú rere sí mi, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.+ Nu àwọn àṣìṣe mi kúrò nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ.+ Sáàmù 103:12 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 12 Bí yíyọ oòrùn ṣe jìnnà sí wíwọ̀ oòrùn,Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa jìnnà sí wa.+ Àìsáyà 1:18 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 18 “Ní báyìí, ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yanjú ọ̀rọ̀ láàárín ara wa,” ni Jèhófà wí.+ “Bí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín tiẹ̀ rí bí aṣọ rírẹ̀dòdò,Wọ́n máa di funfun bíi yìnyín;+Bí wọ́n tiẹ̀ pọ́n bí aṣọ tó pupa yòò,Wọ́n máa dà bí irun àgùntàn. Àìsáyà 43:25 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 25 Èmi, àní èmi ni Ẹni tó ń nu àwọn àṣìṣe* rẹ+ kúrò nítorí tèmi,+Mi ò sì ní rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.+ Jeremáyà 33:8 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 8 Ṣe ni màá wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀bi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n dá sí mi,+ màá sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n àti àwọn àṣìṣe wọn.+ Ìṣe 3:19 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 19 “Nítorí náà, ẹ ronú pìwà dà,+ kí ẹ sì yí pa dà,+ kí Ọlọ́run lè pa àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́,+ kí àwọn àsìkò ìtura lè wá látọ̀dọ̀ Jèhófà fúnra rẹ̀,*
51 Ọlọ́run, ṣojú rere sí mi, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.+ Nu àwọn àṣìṣe mi kúrò nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ.+
18 “Ní báyìí, ẹ wá, ẹ jẹ́ ká yanjú ọ̀rọ̀ láàárín ara wa,” ni Jèhófà wí.+ “Bí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín tiẹ̀ rí bí aṣọ rírẹ̀dòdò,Wọ́n máa di funfun bíi yìnyín;+Bí wọ́n tiẹ̀ pọ́n bí aṣọ tó pupa yòò,Wọ́n máa dà bí irun àgùntàn.
8 Ṣe ni màá wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀bi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n dá sí mi,+ màá sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n àti àwọn àṣìṣe wọn.+
19 “Nítorí náà, ẹ ronú pìwà dà,+ kí ẹ sì yí pa dà,+ kí Ọlọ́run lè pa àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́,+ kí àwọn àsìkò ìtura lè wá látọ̀dọ̀ Jèhófà fúnra rẹ̀,*