17 Lẹ́yìn náà, Ọba Sedekáyà ránṣẹ́ pè é, ọba sì bi í ní ìbéèrè ní bòókẹ́lẹ́ nínú ilé* rẹ̀.+ Ó bi í pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kankan wà látọ̀dọ̀ Jèhófà?” Jeremáyà fèsì pé, “Ó wà!” ó sì fi kún un pé, “A ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Bábílónì!”+
5 Àmọ́ àwọn ọmọ ogun Kálídíà lé wọn, wọ́n sì bá Sedekáyà ní aṣálẹ̀ tó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹ́ríkò.+ Wọ́n gbá a mú, wọ́n sì mú un wá sọ́dọ̀ Nebukadinésárì* ọba Bábílónì ní Ríbúlà+ ní ilẹ̀ Hámátì,+ ibẹ̀ ló sì ti dá a lẹ́jọ́.