29 Àwọn ará Kálídíà tó ń bá ìlú yìí jà máa wọlé wá, wọ́n á sọ iná sí i, wọ́n á sì sun ún kanlẹ̀+ pẹ̀lú àwọn ilé tí àwọn èèyàn náà ti ń rú ẹbọ lórí òrùlé wọn sí Báálì, tí wọ́n sì ti ń da ọrẹ ohun mímu sí àwọn ọlọ́run míì láti mú mi bínú.’+
22 “‘Wò ó, màá pàṣẹ,’ ni Jèhófà wí, ‘màá sì mú wọn pa dà wá sí ìlú yìí, wọ́n á bá a jà, wọ́n á gbà á, wọ́n á sì dáná sun ún;+ màá sọ àwọn ìlú Júdà di ahoro tí ò ní sí ẹnì kankan tí á máa gbé ibẹ̀.’”+