-
2 Kíróníkà 36:15, 16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn ń kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀, ó ń kìlọ̀ fún wọn léraléra, nítorí pé àánú àwọn èèyàn rẹ̀ àti ibùgbé rẹ̀ ń ṣe é. 16 Ṣùgbọ́n wọ́n ń fi àwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ ṣẹ̀sín,+ wọn ò ka ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí,+ wọ́n sì ń fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣe yẹ̀yẹ́,+ títí ìbínú Jèhófà fi ru sí àwọn èèyàn rẹ̀,+ tí ọ̀rọ̀ wọn sì kọjá àtúnṣe.
-
-
Àìsáyà 65:2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
2 Mo ti tẹ́ ọwọ́ mi sí àwọn alágídí láti àárọ̀ ṣúlẹ̀,+
Sí àwọn tó ń rìn ní ọ̀nà tí kò dáa,+
Tí wọ́n ń tẹ̀ lé èrò tiwọn;+
-
Jeremáyà 7:24-26Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 Ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sí mi, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sílẹ̀,+ kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n ń rìn nínú ètekéte* wọn, wọ́n ya alágídí, wọ́n sì ń ṣe ohun tí ọkàn búburú wọn sọ,+ ńṣe ni wọ́n ń pa dà sẹ́yìn, wọn ò lọ síwájú, 25 láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá yín ti jáde kúrò nílẹ̀ Íjíbítì títí di òní.+ Torí náà, mò ń rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín, mò ń rán wọn lójoojúmọ́, mo sì ń rán wọn léraléra.*+ 26 Ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sí mi, wọn kò sì fetí sílẹ̀.+ Kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n ya alágídí,* wọ́n sì ṣe ohun tó burú ju ti àwọn baba ńlá wọn lọ!
-
-
Jeremáyà 35:15Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 Mo sì ń rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín, mò ń rán wọn léraléra,*+ wọ́n ń sọ pé, ‘Ẹ jọ̀wọ́, ẹ yí pa dà, kí kálukú yín kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀,+ kí ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́! Ẹ má ṣe tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì, ẹ má sì sìn wọ́n. Nígbà náà, ẹ ó máa gbé ní ilẹ̀ tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba ńlá yín.’+ Ṣùgbọ́n ẹ kò dẹ etí yín sílẹ̀, ẹ kò sì fetí sí mi.
-
-
-