ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 4:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Ni mo bá sọ pé: “Áà, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ! O ti tan àwọn èèyàn yìí+ àti Jerúsálẹ́mù jẹ pátápátá, o sọ pé, ‘Ẹ máa ní àlàáfíà,’+ nígbà tó jẹ́ pé idà ló wà lọ́rùn wa.”*

  • Jeremáyà 5:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́,+

      Àwọn àlùfáà sì ń fi àṣẹ wọn tẹ àwọn èèyàn lórí ba.

      Àwọn èèyàn mi sì fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀.+

      Àmọ́, kí lẹ máa ṣe nígbà tí òpin bá dé?”

  • Jeremáyà 6:13, 14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 “Látorí ẹni kékeré títí dórí ẹni ńlá, kálukú wọn ń jẹ èrè tí kò tọ́;+

      Látorí wòlíì títí dórí àlùfáà, kálukú wọn ń lu jìbìtì.+

      14 Wọ́n sì ń wo àárẹ̀* àwọn èèyàn mi sàn láàbọ̀,* wọ́n ń sọ pé,

      ‘Àlàáfíà wà! Àlàáfíà wà!’

      Nígbà tí kò sí àlàáfíà.+

  • Jeremáyà 23:16, 17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí:

      “Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún yín.+

      Wọ́n ń tàn yín ni.*

      Ìran tó wá láti inú ọkàn wọn ni wọ́n ń sọ,+

      Kì í ṣe láti ẹnu Jèhófà.+

      17 Léraléra ni wọ́n ń sọ fún àwọn tí kò bọ̀wọ̀ fún mi pé,

      ‘Jèhófà ti sọ pé: “Ẹ máa ní àlàáfíà.”’+

      Wọ́n sì ń sọ fún gbogbo ẹni tó ní agídí ọkàn pé,

      ‘Àjálù kankan kò ní bá yín.’+

  • Jeremáyà 27:8-10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 “‘“‘Tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba èyíkéyìí bá kọ̀ láti sin Ọba Nebukadinésárì ti Bábílónì, tí kò sì fi ọrùn rẹ̀ sábẹ́ àjàgà ọba Bábílónì, ńṣe ni màá fìyà jẹ orílẹ̀-èdè yẹn nípa idà,+ ìyàn àti àjàkálẹ̀ àrùn,’* ni Jèhófà wí, ‘títí màá fi run wọ́n láti ọwọ́ rẹ̀.’

      9 “‘“‘Torí náà, ẹ má fetí sí àwọn wòlíì yín, àwọn woṣẹ́woṣẹ́ yín, àwọn alálàá yín, àwọn onídán yín àti àwọn oníṣẹ́ oṣó yín, tí wọ́n ń sọ fún yín pé: “Ẹ kò ní sin ọba Bábílónì.” 10 Nítorí èké ni wọ́n ń sọ tẹ́lẹ̀ fún yín, kí ẹ lè lọ jìnnà kúrò lórí ilẹ̀ yín, kí n lè fọ́n yín ká, kí ẹ sì ṣègbé.

  • Ìsíkíẹ́lì 13:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Gbogbo èyí jẹ́ torí pé wọ́n ti ṣi àwọn èèyàn mi lọ́nà, bí wọ́n ṣe ń sọ pé, “Àlàáfíà wà!” nígbà tí kò sí àlàáfíà.+ Tí wọ́n bá mọ ògiri tí kò lágbára, wọ́n á kùn ún ní ẹfun.’*+

  • Míkà 3:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Àwọn olórí* rẹ̀ ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kí wọ́n tó dájọ́,+

      Àwọn àlùfáà rẹ̀ ń gba owó kí wọ́n tó kọ́ni,+

      Àwọn wòlíì rẹ̀ ń gba owó* kí wọ́n tó woṣẹ́.+

      Síbẹ̀ wọ́n gbára lé Jèhófà,* wọ́n ń sọ pé:

      “Ṣebí Jèhófà wà pẹ̀lú wa?+

      Àjálù kankan ò lè dé bá wa.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́