-
Jeremáyà 27:8-10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 “‘“‘Tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba èyíkéyìí bá kọ̀ láti sin Ọba Nebukadinésárì ti Bábílónì, tí kò sì fi ọrùn rẹ̀ sábẹ́ àjàgà ọba Bábílónì, ńṣe ni màá fìyà jẹ orílẹ̀-èdè yẹn nípa idà,+ ìyàn àti àjàkálẹ̀ àrùn,’* ni Jèhófà wí, ‘títí màá fi run wọ́n láti ọwọ́ rẹ̀.’
9 “‘“‘Torí náà, ẹ má fetí sí àwọn wòlíì yín, àwọn woṣẹ́woṣẹ́ yín, àwọn alálàá yín, àwọn onídán yín àti àwọn oníṣẹ́ oṣó yín, tí wọ́n ń sọ fún yín pé: “Ẹ kò ní sin ọba Bábílónì.” 10 Nítorí èké ni wọ́n ń sọ tẹ́lẹ̀ fún yín, kí ẹ lè lọ jìnnà kúrò lórí ilẹ̀ yín, kí n lè fọ́n yín ká, kí ẹ sì ṣègbé.
-