-
1 Àwọn Ọba 8:33, 34Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
33 “Nígbà tí ọ̀tá bá ṣẹ́gun àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì torí pé wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ sí ọ,+ tí wọ́n wá pa dà sọ́dọ̀ rẹ, tí wọ́n gbé orúkọ rẹ ga,+ tí wọ́n gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀ ọ́ nínú ilé yìí pé kí o ṣojú rere sí àwọn,+ 34 nígbà náà, kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì jì wọ́n, kí o sì mú wọn pa dà wá sí ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wọn.+
-
-
Jeremáyà 7:3Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: “Ẹ tún ọ̀nà yín àti ìwà yín ṣe, màá sì jẹ́ kí ẹ máa gbé ibí yìí.+
-