ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Àwọn Ọba 8:33, 34
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 33 “Nígbà tí ọ̀tá bá ṣẹ́gun àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì torí pé wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ sí ọ,+ tí wọ́n wá pa dà sọ́dọ̀ rẹ, tí wọ́n gbé orúkọ rẹ ga,+ tí wọ́n gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀ ọ́ nínú ilé yìí pé kí o ṣojú rere sí àwọn,+ 34 nígbà náà, kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì jì wọ́n, kí o sì mú wọn pa dà wá sí ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wọn.+

  • Sáàmù 106:45
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 45 Nítorí wọn, á rántí májẹ̀mú rẹ̀,

      Àánú á sì ṣe é* nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tó ga tí kì í sì í yẹ̀.*+

  • Jeremáyà 7:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: “Ẹ tún ọ̀nà yín àti ìwà yín ṣe, màá sì jẹ́ kí ẹ máa gbé ibí yìí.+

  • Jeremáyà 26:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Bóyá wọ́n á fetí sílẹ̀, tí kálukú wọn á yí pa dà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn, tí màá sì pèrò dà* lórí àjálù tí mo fẹ́ mú bá wọn nítorí ìwà ibi wọn.+

  • Ìsíkíẹ́lì 18:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 “‘Àmọ́, bí ẹni burúkú bá yí pa dà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, tó ń pa àwọn àṣẹ mi mọ́, tó ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó jẹ́ òdodo, ó dájú pé yóò máa wà láàyè. Kò ní kú.+

  • Jóẹ́lì 2:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Ọkàn yín ni kí ẹ fà ya,+ kì í ṣe ẹ̀wù yín,+

      Kí ẹ sì pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run yín,

      Torí ó ń gba tẹni rò,* ó jẹ́ aláàánú, kì í tètè bínú,+ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀ gidigidi,+

      Òun yóò sì pèrò dà* nípa àjálù náà.

  • Jónà 3:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Àwọn ará ìlú Nínéfè wá gba Ọlọ́run gbọ́,+ wọ́n kéde pé kí gbogbo ìlú gbààwẹ̀, wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀,* látorí ẹni tó tóbi jù dórí ẹni tó kéré jù.

  • Jónà 3:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Nígbà tí Ọlọ́run tòótọ́ rí ohun tí wọ́n ṣe, bí wọ́n ṣe yí ìwà burúkú wọn pa dà,+ ó pèrò dà* nípa àjálù tó sọ pé òun máa mú kó dé bá wọn, kò sì jẹ́ kó ṣẹlẹ̀ sí wọn.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́