14 Jèhófà wá sọ fún mi pé: “Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni àwọn wòlíì náà ń sọ ní orúkọ mi.+ Mi ò rán wọn, bẹ́ẹ̀ ni mi ò pàṣẹ fún wọn, mi ò sì bá wọn sọ̀rọ̀.+ Ìran èké àti ìwoṣẹ́ asán àti ẹ̀tàn ọkàn wọn ni wọ́n ń sọ tẹ́lẹ̀ fún yín.+
21 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí nípa Áhábù ọmọ Koláyà àti nípa Sedekáyà ọmọ Maaseáyà, àwọn tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín ní orúkọ mi,+ ‘Wò ó, màá fi wọ́n lé ọwọ́ Nebukadinésárì* ọba Bábílónì, á sì pa wọ́n lójú yín.