12 Tí wọ́n bá gbààwẹ̀, mi ò ní fetí sí ẹ̀bẹ̀ wọn,+ tí wọ́n bá sì fi odindi ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà rúbọ, inú mi ò ní dùn sí wọn,+ nítorí pé idà àti ìyàn àti àjàkálẹ̀ àrùn* ni màá fi pa wọ́n.”+
9 Idà àti ìyàn pẹ̀lú àjàkálẹ̀ àrùn ni yóò pa àwọn tó bá dúró nínú ìlú yìí. Àmọ́ ẹni tó bá jáde, tó sì fi ara rẹ̀ lé ọwọ́ àwọn ará Kálídíà tí wọ́n dó tì yín, á máa wà láàyè, á sì jèrè ẹ̀mí rẹ̀.”’*+