ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 23:8, 9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Lẹ́yìn náà, ó kó gbogbo àwọn àlùfáà jáde kúrò ní àwọn ìlú Júdà, ó sì sọ àwọn ibi gíga tí àwọn àlùfáà ti ń mú ẹbọ rú èéfín di ibi tí kò ṣeé lò fún ìjọsìn, láti Gébà+ títí dé Bíá-ṣébà.+ Ó tún wó àwọn ibi gíga ẹnubodè tó wà ní ibi àtiwọ ẹnubodè Jóṣúà olórí ìlú náà, èyí tó wà lápá òsì tí èèyàn bá wọ ẹnubodè ìlú náà. 9 Àwọn àlùfáà ibi gíga kò ṣiṣẹ́ níbi pẹpẹ Jèhófà tó wà ní Jerúsálẹ́mù,+ àmọ́ wọ́n máa ń jẹ búrẹ́dì aláìwú pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn.

  • 2 Kíróníkà 29:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 29 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni Hẹsikáyà+ nígbà tó jọba, ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n (29) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Ábíjà ọmọ Sekaráyà.+

  • 2 Kíróníkà 29:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin ọmọ Léfì. Ní báyìí, ẹ ya ara yín sí mímọ́,+ kí ẹ ya ilé Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá yín sí mímọ́, kí ẹ sì mú ohun àìmọ́ kúrò nínú ibi mímọ́.+

  • Nehemáyà 9:34
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 34 Ní ti àwọn ọba wa, àwọn ìjòyè wa, àwọn àlùfáà wa àti àwọn baba ńlá wa, wọn ò pa Òfin rẹ mọ́, wọn ò sì fiyè sí àwọn àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìránnilétí* rẹ tí o fi kìlọ̀ fún wọn.

  • Jeremáyà 23:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 “Nítorí pé wòlíì àti àlùfáà ti di eléèérí.*+

      Kódà, mo ti rí ìwà búburú wọn nínú ilé mi,”+ ni Jèhófà wí.

  • Ìsíkíẹ́lì 8:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Ó wá sọ fún mi pé: “Ọmọ èèyàn, jọ̀ọ́ gbójú sókè kí o wo àríwá.” Torí náà, mo wo àríwá, mo sì rí ère* owú náà ní àríwá ẹnubodè pẹpẹ.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́