-
Ẹ́sírà 1:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
1 Ní ọdún kìíní Kírúsì+ ọba Páṣíà, kí ọ̀rọ̀ tí Jèhófà gbẹnu Jeremáyà+ sọ lè ṣẹ, Jèhófà ta ẹ̀mí Kírúsì ọba Páṣíà jí láti kéde ní gbogbo ìjọba rẹ̀, ó sì tún kọ ọ́ sílẹ̀+ pé:
2 “Ohun tí Kírúsì ọba Páṣíà sọ nìyí, ‘Jèhófà Ọlọ́run ọ̀run ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé,+ ó sì pàṣẹ fún mi pé kí n kọ́ ilé fún òun ní Jerúsálẹ́mù,+ tó wà ní Júdà.
-
-
Jeremáyà 50:9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Nítorí wò ó, màá gbé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti ilẹ̀ àríwá
Màá sì mú kí wọ́n gbéjà ko Bábílónì.+
Wọ́n á tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti gbógun tì í;
Ibẹ̀ ni wọ́n á ti gbà á.
-