6 “Lẹ́yìn èyí, mò ń wò, sì wò ó! ẹranko míì tó dà bí àmọ̀tẹ́kùn,+ àmọ́ tó ní ìyẹ́ mẹ́rin bíi ti ẹyẹ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ẹranko náà ní orí mẹ́rin,+ a sì fún un ní àṣẹ láti ṣàkóso.
8 Òbúkọ náà wá gbé ara rẹ̀ ga kọjá ààlà, àmọ́ gbàrà tó di alágbára, ìwo ńlá náà ṣẹ́; ìwo mẹ́rin tó hàn kedere sì jáde dípò ìwo kan ṣoṣo náà, wọ́n dojú kọ atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.+