ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 23:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Júdà máa rí ìgbàlà ní ìgbà ayé rẹ̀,+ Ísírẹ́lì sì máa wà ní ààbò.+ Orúkọ tí a ó sì máa pè é ni, Jèhófà Ni Òdodo Wa.”+

  • Ìsíkíẹ́lì 28:25, 26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 25 “‘Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: “Nígbà tí mo bá tún kó ilé Ísírẹ́lì jọ láti àárín àwọn èèyàn tí wọ́n fọ́n ká sí,+ màá fi hàn pé mo jẹ́ mímọ́ láàárín wọn lójú àwọn orílẹ̀-èdè.+ Wọ́n á sì máa gbé lórí ilẹ̀ wọn+ tí mo fún Jékọ́bù ìránṣẹ́ mi.+ 26 Wọn yóò máa gbé ibẹ̀, ààbò yóò sì wà lórí wọn,+ wọ́n á kọ́ ilé, wọ́n á gbin ọgbà àjàrà,+ nígbà tí mo bá ṣèdájọ́ gbogbo àwọn tó yí wọn ká tó ń fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,+ ààbò yóò wà lórí wọn; wọ́n á sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà Ọlọ́run wọn.”’”

  • Ìsíkíẹ́lì 37:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 “Kí o wá sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: “Èmi yóò mú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n lọ, èmi yóò kó wọn jọ láti ibi gbogbo, èmi yóò sì mú wọn wá sórí ilẹ̀ wọn.+

  • Émọ́sì 9:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Màá kó àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì tó wà ní ìgbèkùn pa dà,+

      Wọ́n á tún àwọn ìlú tó ti di ahoro kọ́, wọ́n á sì máa gbé inú wọn;+

      Wọ́n á gbin ọgbà àjàrà, wọ́n á sì mu wáìnì wọn,+

      Wọ́n á ṣe ọgbà, wọ́n á sì jẹ èso wọn.’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́