-
Ìsíkíẹ́lì 28:25, 26Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
25 “‘Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: “Nígbà tí mo bá tún kó ilé Ísírẹ́lì jọ láti àárín àwọn èèyàn tí wọ́n fọ́n ká sí,+ màá fi hàn pé mo jẹ́ mímọ́ láàárín wọn lójú àwọn orílẹ̀-èdè.+ Wọ́n á sì máa gbé lórí ilẹ̀ wọn+ tí mo fún Jékọ́bù ìránṣẹ́ mi.+ 26 Wọn yóò máa gbé ibẹ̀, ààbò yóò sì wà lórí wọn,+ wọ́n á kọ́ ilé, wọ́n á gbin ọgbà àjàrà,+ nígbà tí mo bá ṣèdájọ́ gbogbo àwọn tó yí wọn ká tó ń fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,+ ààbò yóò wà lórí wọn; wọ́n á sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà Ọlọ́run wọn.”’”
-