ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Dáníẹ́lì 9:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 “Ó máa mú kí májẹ̀mú náà wà lẹ́nu iṣẹ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀, fún ọ̀sẹ̀ kan; ní ìdajì ọ̀sẹ̀ náà, ó máa mú kí ẹbọ àti ọrẹ dópin.+

      “Ẹni tó ń sọ nǹkan di ahoro máa wà lórí ìyẹ́ àwọn ohun ìríra;+ títí dìgbà ìparun, a máa da ohun tí a pinnu sórí ẹni tó ti di ahoro pẹ̀lú.”

  • Dáníẹ́lì 11:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 Àwọn ọmọ ogun* máa dìde, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀; wọ́n máa sọ ibi mímọ́, ibi ààbò, di aláìmọ́,+ wọ́n sì máa mú ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nígbà gbogbo* kúrò.+

      “Wọ́n máa gbé ohun ìríra tó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀.+

  • Dáníẹ́lì 12:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 “Látìgbà tí a bá ti mú ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nígbà gbogbo*+ kúrò, tí a sì ti gbé ohun ìríra tó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀,+ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti àádọ́rùn-ún (1,290) ọjọ́ máa wà.

  • Máàkù 13:14-18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 “Àmọ́ tí ẹ bá tajú kán rí ohun ìríra tó ń fa ìsọdahoro,+ tó dúró ní ibi tí kò yẹ (kí òǹkàwé lo òye), nígbà náà, kí àwọn tó wà ní Jùdíà bẹ̀rẹ̀ sí í sá lọ sí àwọn òkè.+ 15 Kí ẹni tó wà lórí ilé má sọ̀ kalẹ̀ tàbí kó wọlé lọ mú ohunkóhun kúrò nínú ilé rẹ̀; 16 kí ẹni tó wà ní pápá má sì pa dà sí àwọn ohun tó wà lẹ́yìn láti mú aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀. 17 Ó mà ṣe o, fún àwọn aláboyún àti àwọn tó ń tọ́ ọmọ jòjòló ní àwọn ọjọ́ yẹn o!+ 18 Ẹ máa gbàdúrà kó má lọ bọ́ sí ìgbà òtútù;

  • Lúùkù 21:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 “Àmọ́, tí ẹ bá rí i tí àwọn ọmọ ogun pàgọ́ yí Jerúsálẹ́mù ká,+ nígbà náà, kí ẹ mọ̀ pé àkókò tó máa dahoro ti sún mọ́lé.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́