-
Mátíù 10:1Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 Ó pe àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá (12), ó sì fún wọn ní àṣẹ lórí àwọn ẹ̀mí àìmọ́,+ kí wọ́n lè lé àwọn ẹ̀mí yìí jáde, kí wọ́n sì wo onírúurú àìsàn àti onírúurú àìlera sàn.
-
-
Lúùkù 9:1-6Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Ó wá pe àwọn Méjìlá náà jọ, ó fún wọn ní agbára àti àṣẹ lórí gbogbo ẹ̀mí èṣù,+ kí wọ́n sì máa ṣe ìwòsàn.+ 2 Ó rán wọn jáde láti wàásù Ìjọba Ọlọ́run, kí wọ́n sì máa múni lára dá, 3 ó sọ fún wọn pé: “Ẹ má ṣe gbé ohunkóhun dání fún ìrìn àjò náà, ì báà jẹ́ ọ̀pá, àpò oúnjẹ, oúnjẹ tàbí owó;* ẹ má sì mú aṣọ méjì.*+ 4 Àmọ́ ibikíbi tí ẹ bá ti wọ ilé kan, ẹ dúró síbẹ̀, kí ẹ sì lọ láti ibẹ̀.+ 5 Ibikíbi tí àwọn èèyàn ò bá sì ti gbà yín, tí ẹ bá ń kúrò ní ìlú yẹn, ẹ gbọn iyẹ̀pẹ̀ ẹsẹ̀ yín dà nù, kó lè jẹ́ ẹ̀rí lòdì sí wọn.”+ 6 Lẹ́yìn náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í lọ káàkiri agbègbè náà láti abúlé dé abúlé, wọ́n ń kéde ìhìn rere, wọ́n sì ń ṣe ìwòsàn níbi gbogbo.+
-