28 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin lẹ ti dúró tì mí+ nígbà àdánwò;+ 29 mo sì bá yín dá májẹ̀mú fún ìjọba kan, bí Baba mi ṣe bá mi dá májẹ̀mú,+ 30 kí ẹ lè máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ní tábìlì mi nínú Ìjọba mi,+ kí ẹ sì jókòó lórí ìtẹ́+ láti ṣèdájọ́ ẹ̀yà méjìlá (12) Ísírẹ́lì.+