-
Jẹ́nẹ́sísì 6:1-4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Nígbà tí àwọn èèyàn bẹ̀rẹ̀ sí í pọ̀ lórí ilẹ̀, tí wọ́n sì ń bí àwọn ọmọbìnrin, 2 àwọn ọmọ Ọlọ́run tòótọ́*+ wá bẹ̀rẹ̀ sí í kíyè sí i pé àwọn ọmọbìnrin èèyàn rẹwà. Wọ́n sì ń fi gbogbo ẹni tó wù wọ́n ṣe aya. 3 Jèhófà wá sọ pé: “Ẹ̀mí mi ò ní gba èèyàn láyè títí láé,+ torí ẹlẹ́ran ara ni.* Torí náà, ọgọ́fà (120) ọdún ni ọjọ́ rẹ̀ yóò jẹ́.”+
4 Àwọn Néfílímù* wà ní ayé nígbà yẹn àti lẹ́yìn ìgbà yẹn. Ní àkókò yẹn, àwọn ọmọ Ọlọ́run tòótọ́ ń bá àwọn ọmọbìnrin èèyàn lò pọ̀, wọ́n sì bí àwọn ọmọ fún wọn. Àwọn ni alágbára ayé ìgbà yẹn, àwọn ọkùnrin olókìkí.
-