7 Kí àlùfáà náà tún fi lára ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àwọn ìwo pẹpẹ tùràrí onílọ́fínńdà,+ tó wà níwájú Jèhófà nínú àgọ́ ìpàdé; kó sì da gbogbo ìyókù ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun,+ tó wà ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
3 Áńgẹ́lì míì dé, ó dúró níbi pẹpẹ,+ ó gbé àwo tùràrí tí wọ́n fi wúrà ṣe* dání, a sì fún un ní tùràrí tó pọ̀ gan-an+ pé kó sun ún lórí pẹpẹ tí wọ́n fi wúrà ṣe+ tó wà níwájú ìtẹ́ náà bí gbogbo àwọn ẹni mímọ́ ṣe ń gbàdúrà.