ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 10
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Sámúẹ́lì

      • Ó ṣẹ́gun Ámónì àti Síríà (1-19)

2 Sámúẹ́lì 10:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 19:36, 38; Ond 10:7; 11:12, 33; 1Sa 11:1
  • +1Kr 19:1-5

2 Sámúẹ́lì 10:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 19:27

2 Sámúẹ́lì 10:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 18:21

2 Sámúẹ́lì 10:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn ọkùnrin Tóbù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 13:21
  • +2Sa 8:5
  • +Joṣ 13:13
  • +1Kr 19:6, 7

2 Sámúẹ́lì 10:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 23:8; 1Kr 19:8, 9

2 Sámúẹ́lì 10:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn ọkùnrin Tóbù.”

2 Sámúẹ́lì 10:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 19:10-13

2 Sámúẹ́lì 10:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “sí ọwọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 26:6; 2Sa 2:18; 23:18; 1Kr 2:15, 16
  • +Nọ 21:24

2 Sámúẹ́lì 10:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:6
  • +Sm 37:5; 44:5; Owe 29:25

2 Sámúẹ́lì 10:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 19:14, 15

2 Sámúẹ́lì 10:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 19:16

2 Sámúẹ́lì 10:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, Yúfírétì.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:3-5
  • +Jẹ 15:18; Ẹk 23:31

2 Sámúẹ́lì 10:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 19:17-19

2 Sámúẹ́lì 10:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 20:1; Sm 18:37, 38

2 Sámúẹ́lì 10:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 15:18; Di 20:10, 11

Àwọn míì

2 Sám. 10:1Jẹ 19:36, 38; Ond 10:7; 11:12, 33; 1Sa 11:1
2 Sám. 10:11Kr 19:1-5
2 Sám. 10:4Le 19:27
2 Sám. 10:5Joṣ 18:21
2 Sám. 10:6Nọ 13:21
2 Sám. 10:62Sa 8:5
2 Sám. 10:6Joṣ 13:13
2 Sám. 10:61Kr 19:6, 7
2 Sám. 10:72Sa 23:8; 1Kr 19:8, 9
2 Sám. 10:91Kr 19:10-13
2 Sám. 10:101Sa 26:6; 2Sa 2:18; 23:18; 1Kr 2:15, 16
2 Sám. 10:10Nọ 21:24
2 Sám. 10:12Di 31:6
2 Sám. 10:12Sm 37:5; 44:5; Owe 29:25
2 Sám. 10:131Kr 19:14, 15
2 Sám. 10:151Kr 19:16
2 Sám. 10:162Sa 8:3-5
2 Sám. 10:16Jẹ 15:18; Ẹk 23:31
2 Sám. 10:171Kr 19:17-19
2 Sám. 10:18Di 20:1; Sm 18:37, 38
2 Sám. 10:19Jẹ 15:18; Di 20:10, 11
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Sámúẹ́lì 10:1-19

Sámúẹ́lì Kejì

10 Nígbà tó yá, ọba àwọn ọmọ Ámónì+ kú, Hánúnì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.+ 2 Dáfídì bá sọ pé: “Màá fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí Hánúnì ọmọ Náháṣì, bí bàbá rẹ̀ ṣe fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi.” Torí náà, Dáfídì rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láti lọ tù ú nínú nítorí bàbá rẹ̀ tó kú. Àmọ́ nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì dé ilẹ̀ àwọn ọmọ Ámónì, 3 àwọn ìjòyè àwọn ọmọ Ámónì sọ fún Hánúnì olúwa wọn pé: “Ṣé o rò pé torí kí Dáfídì lè bọlá fún bàbá rẹ ló ṣe rán àwọn olùtùnú sí ọ? Ǹjẹ́ kì í ṣe torí kí Dáfídì lè wo inú ìlú yìí, kí ó ṣe amí rẹ̀, kí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ ló ṣe rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sí ọ?” 4 Nítorí náà, Hánúnì mú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, ó fá apá kan irùngbọ̀n+ wọn dà nù, ó gé ẹ̀wù wọn ní ààbọ̀ dé ìdí, ó sì ní kí wọ́n máa lọ. 5 Nígbà tí Dáfídì gbọ́, kíá ló rán àwọn ọkùnrin kan lọ pàdé wọn, nítorí wọ́n ti dójú ti àwọn ọkùnrin náà gan-an; ọba sì sọ fún wọn pé: “Ẹ dúró sí Jẹ́ríkò+ títí irùngbọ̀n yín á fi hù pa dà, lẹ́yìn náà kí ẹ pa dà wálé.”

6 Nígbà tó yá, àwọn ọmọ Ámónì rí i pé àwọn ti di ẹni ìkórìíra lójú Dáfídì, torí náà àwọn ọmọ Ámónì ránṣẹ́ sí àwọn ará Síríà tó wà ní Bẹti-réhóbù+ àti àwọn ará Síríà tó wà ní Sóbà,+ wọ́n sì háyà ọ̀kẹ́ kan (20,000) àwọn ọmọ ogun tó ń fẹsẹ̀ rìn lọ́dọ̀ wọn; àti lọ́dọ̀ ọba Máákà,+ ẹgbẹ̀rún kan (1,000) ọkùnrin; àti láti Íṣítóbù,* ẹgbẹ̀rún méjìlá (12,000) ọkùnrin.+ 7 Nígbà tí Dáfídì gbọ́, ó rán Jóábù lọ àti gbogbo àwọn ọmọ ogun títí kan àwọn jagunjagun rẹ̀ tó lákíkanjú+ jù lọ. 8 Àwọn ọmọ Ámónì jáde lọ, wọ́n sì tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ ní àtiwọ ẹnubodè ìlú, àmọ́ àwọn ará Síríà tó wà ní Sóbà àti ní Réhóbù pẹ̀lú Íṣítóbù* àti Máákà wà lórí pápá.

9 Nígbà tí Jóábù rí i pé wọ́n ń gbé ogun bọ̀ níwájú àti lẹ́yìn, ó yan lára àwọn ọmọ ogun tó dára jù lọ ní Ísírẹ́lì, ó sì tò wọ́n lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé àwọn ará Síríà.+ 10 Ó fi àwọn tó kù lára àwọn ọkùnrin náà sábẹ́ àṣẹ* Ábíṣáì+ ẹ̀gbọ́n rẹ̀, kí ó lè tò wọ́n lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé àwọn ọmọ Ámónì.+ 11 Ó wá sọ pé: “Tí ọwọ́ àwọn ará Síríà bá le jù fún mi, kí o wá gbà mí sílẹ̀; àmọ́ tí ọwọ́ àwọn ọmọ Ámónì bá le jù fún ọ, màá wá gbà ọ́ sílẹ̀. 12 Kí a jẹ́ alágbára, kí a sì ní ìgboyà+ nítorí àwọn èèyàn wa àti àwọn ìlú Ọlọ́run wa, Jèhófà yóò sì ṣe ohun tó dára ní ojú rẹ̀.”+

13 Ìgbà náà ni Jóábù àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ jáde lọ pàdé àwọn ará Síríà lójú ogun, wọ́n sì sá kúrò níwájú rẹ̀.+ 14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ámónì rí i pé àwọn ará Síríà ti fẹsẹ̀ fẹ, àwọn náà sá kúrò níwájú Ábíṣáì, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Lẹ́yìn náà, Jóábù pa dà látọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ámónì, ó sì wá sí Jerúsálẹ́mù.

15 Nígbà tí àwọn ará Síríà rí i pé Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn, wọ́n túnra mú.+ 16 Nítorí náà, Hadadésà+ ránṣẹ́ sí àwọn ará Síríà tó wà ní agbègbè Odò,*+ lẹ́yìn náà, wọ́n wá sí Hélámù, Ṣóbákì olórí àwọn ọmọ ogun Hadadésà ló sì ń darí wọn.

17 Nígbà tí wọ́n ròyìn fún Dáfídì, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ, ó sọdá Jọ́dánì, ó sì wá sí Hélámù. Ìgbà náà ni àwọn ará Síríà to ara wọn lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé Dáfídì, wọ́n sì bá a jà.+ 18 Àmọ́, àwọn ará Síríà sá kúrò níwájú Ísírẹ́lì; Dáfídì sì pa ọgọ́rùn-ún méje (700) àwọn tó ń gun kẹ̀kẹ́ ẹṣin àti ọ̀kẹ́ méjì (40,000) àwọn agẹṣin ará Síríà, ó ṣá Ṣóbákì olórí àwọn ọmọ ogun wọn balẹ̀, ó sì kú síbẹ̀.+ 19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba àti àwọn ìránṣẹ́ Hadadésà rí i pé Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn, wọ́n tètè wá àlàáfíà lọ́dọ̀ Ísírẹ́lì, wọ́n sì di ọmọ abẹ́ wọn;+ ẹ̀rù wá ń ba àwọn ará Síríà láti tún ran àwọn ọmọ Ámónì lọ́wọ́.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́