Sámúẹ́lì Kejì
10 Nígbà tó yá, ọba àwọn ọmọ Ámónì+ kú, Hánúnì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.+ 2 Dáfídì bá sọ pé: “Màá fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí Hánúnì ọmọ Náháṣì, bí bàbá rẹ̀ ṣe fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi.” Torí náà, Dáfídì rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láti lọ tù ú nínú nítorí bàbá rẹ̀ tó kú. Àmọ́ nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì dé ilẹ̀ àwọn ọmọ Ámónì, 3 àwọn ìjòyè àwọn ọmọ Ámónì sọ fún Hánúnì olúwa wọn pé: “Ṣé o rò pé torí kí Dáfídì lè bọlá fún bàbá rẹ ló ṣe rán àwọn olùtùnú sí ọ? Ǹjẹ́ kì í ṣe torí kí Dáfídì lè wo inú ìlú yìí, kí ó ṣe amí rẹ̀, kí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ ló ṣe rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sí ọ?” 4 Nítorí náà, Hánúnì mú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, ó fá apá kan irùngbọ̀n+ wọn dà nù, ó gé ẹ̀wù wọn ní ààbọ̀ dé ìdí, ó sì ní kí wọ́n máa lọ. 5 Nígbà tí Dáfídì gbọ́, kíá ló rán àwọn ọkùnrin kan lọ pàdé wọn, nítorí wọ́n ti dójú ti àwọn ọkùnrin náà gan-an; ọba sì sọ fún wọn pé: “Ẹ dúró sí Jẹ́ríkò+ títí irùngbọ̀n yín á fi hù pa dà, lẹ́yìn náà kí ẹ pa dà wálé.”
6 Nígbà tó yá, àwọn ọmọ Ámónì rí i pé àwọn ti di ẹni ìkórìíra lójú Dáfídì, torí náà àwọn ọmọ Ámónì ránṣẹ́ sí àwọn ará Síríà tó wà ní Bẹti-réhóbù+ àti àwọn ará Síríà tó wà ní Sóbà,+ wọ́n sì háyà ọ̀kẹ́ kan (20,000) àwọn ọmọ ogun tó ń fẹsẹ̀ rìn lọ́dọ̀ wọn; àti lọ́dọ̀ ọba Máákà,+ ẹgbẹ̀rún kan (1,000) ọkùnrin; àti láti Íṣítóbù,* ẹgbẹ̀rún méjìlá (12,000) ọkùnrin.+ 7 Nígbà tí Dáfídì gbọ́, ó rán Jóábù lọ àti gbogbo àwọn ọmọ ogun títí kan àwọn jagunjagun rẹ̀ tó lákíkanjú+ jù lọ. 8 Àwọn ọmọ Ámónì jáde lọ, wọ́n sì tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ ní àtiwọ ẹnubodè ìlú, àmọ́ àwọn ará Síríà tó wà ní Sóbà àti ní Réhóbù pẹ̀lú Íṣítóbù* àti Máákà wà lórí pápá.
9 Nígbà tí Jóábù rí i pé wọ́n ń gbé ogun bọ̀ níwájú àti lẹ́yìn, ó yan lára àwọn ọmọ ogun tó dára jù lọ ní Ísírẹ́lì, ó sì tò wọ́n lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé àwọn ará Síríà.+ 10 Ó fi àwọn tó kù lára àwọn ọkùnrin náà sábẹ́ àṣẹ* Ábíṣáì+ ẹ̀gbọ́n rẹ̀, kí ó lè tò wọ́n lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé àwọn ọmọ Ámónì.+ 11 Ó wá sọ pé: “Tí ọwọ́ àwọn ará Síríà bá le jù fún mi, kí o wá gbà mí sílẹ̀; àmọ́ tí ọwọ́ àwọn ọmọ Ámónì bá le jù fún ọ, màá wá gbà ọ́ sílẹ̀. 12 Kí a jẹ́ alágbára, kí a sì ní ìgboyà+ nítorí àwọn èèyàn wa àti àwọn ìlú Ọlọ́run wa, Jèhófà yóò sì ṣe ohun tó dára ní ojú rẹ̀.”+
13 Ìgbà náà ni Jóábù àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ jáde lọ pàdé àwọn ará Síríà lójú ogun, wọ́n sì sá kúrò níwájú rẹ̀.+ 14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ámónì rí i pé àwọn ará Síríà ti fẹsẹ̀ fẹ, àwọn náà sá kúrò níwájú Ábíṣáì, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Lẹ́yìn náà, Jóábù pa dà látọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ámónì, ó sì wá sí Jerúsálẹ́mù.
15 Nígbà tí àwọn ará Síríà rí i pé Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn, wọ́n túnra mú.+ 16 Nítorí náà, Hadadésà+ ránṣẹ́ sí àwọn ará Síríà tó wà ní agbègbè Odò,*+ lẹ́yìn náà, wọ́n wá sí Hélámù, Ṣóbákì olórí àwọn ọmọ ogun Hadadésà ló sì ń darí wọn.
17 Nígbà tí wọ́n ròyìn fún Dáfídì, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ, ó sọdá Jọ́dánì, ó sì wá sí Hélámù. Ìgbà náà ni àwọn ará Síríà to ara wọn lọ́wọ̀ọ̀wọ́ láti pàdé Dáfídì, wọ́n sì bá a jà.+ 18 Àmọ́, àwọn ará Síríà sá kúrò níwájú Ísírẹ́lì; Dáfídì sì pa ọgọ́rùn-ún méje (700) àwọn tó ń gun kẹ̀kẹ́ ẹṣin àti ọ̀kẹ́ méjì (40,000) àwọn agẹṣin ará Síríà, ó ṣá Ṣóbákì olórí àwọn ọmọ ogun wọn balẹ̀, ó sì kú síbẹ̀.+ 19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba àti àwọn ìránṣẹ́ Hadadésà rí i pé Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn, wọ́n tètè wá àlàáfíà lọ́dọ̀ Ísírẹ́lì, wọ́n sì di ọmọ abẹ́ wọn;+ ẹ̀rù wá ń ba àwọn ará Síríà láti tún ran àwọn ọmọ Ámónì lọ́wọ́.