ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Orin Sólómọ́nì 5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Orin Sólómọ́nì

    • Ọ̀DỌ́BÌNRIN ṢÚLÁMÁÍTÌ WÀ NÍ JERÚSÁLẸ́MÙ (3:6–8:4)

Orin Sólómọ́nì 5:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 4:16
  • +Sol 4:13, 14
  • +Sol 4:11
  • +Sol 1:2

Orin Sólómọ́nì 5:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 3:1
  • +Lk 2:8

Orin Sólómọ́nì 5:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Mo fẹ́rẹ̀ẹ́ dá kú.”

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “Mo fẹ́rẹ̀ẹ́ dá kú nígbà tó sọ̀rọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 3:1, 3

Orin Sólómọ́nì 5:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “aṣọ ìbòjú.”

Orin Sólómọ́nì 5:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “dà bí òṣùṣù èso déètì.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jí!,

    1/8/1997, ojú ìwé 25

Orin Sólómọ́nì 5:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “létí orísun omi.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    1/15/2015, ojú ìwé 30

    11/15/2006, ojú ìwé 19

Orin Sólómọ́nì 5:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 6:2
  • +Sol 1:13

Orin Sólómọ́nì 5:14

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2006, ojú ìwé 19-20

Orin Sólómọ́nì 5:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 92:12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2006, ojú ìwé 19-20

Orin Sólómọ́nì 5:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Òkè ẹnu.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 2:3

Àwọn míì

Orin Sól. 5:1Sol 4:16
Orin Sól. 5:1Sol 4:13, 14
Orin Sól. 5:1Sol 4:11
Orin Sól. 5:1Sol 1:2
Orin Sól. 5:2Sol 3:1
Orin Sól. 5:2Lk 2:8
Orin Sól. 5:6Sol 3:1, 3
Orin Sól. 5:13Sol 6:2
Orin Sól. 5:13Sol 1:13
Orin Sól. 5:15Sm 92:12
Orin Sól. 5:16Sol 2:3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Orin Sólómọ́nì 5:1-16

Orin Sólómọ́nì

5 “Mo ti wọnú ọgbà mi,+

Ìwọ arábìnrin mi, ìyàwó mi.

Mo ti já òjíá mi àti ewéko olóòórùn dídùn mi.+

Mo ti jẹ afárá oyin mi àti oyin mi;

Mo ti mu wáìnì mi àti wàrà mi.”+

“Ẹ jẹun, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ ọ̀wọ́n!

Ẹ mu ìfẹ́,+ kí ẹ sì yó!”

 2 “Mo ti sùn lọ, àmọ́ ọkàn mi ò sùn.+

Mo gbọ́ ìró olólùfẹ́ mi tó ń kan ilẹ̀kùn!”

‘Ṣílẹ̀kùn fún mi, arábìnrin mi, olólùfẹ́ mi,

Àdàbà mi, ẹni tí ẹwà rẹ̀ ò lábùlà!

Torí ìrì ti sẹ̀ sí mi lórí,

Ìrì òru+ ti mú kí irun mi tutù.’

 3 Mo ti bọ́ aṣọ mi.

Ṣé kí n tún wọ̀ ọ́ pa dà ni?

Mo ti fọ ẹsẹ̀ mi.

Ṣé kí n tún jẹ́ kó dọ̀tí ni?

 4 Olólùfẹ́ mi mú ọwọ́ kúrò lára ihò ilẹ̀kùn,

Ọkàn mi sì túbọ̀ fà sí i.

 5 Mo dìde kí n lè ṣílẹ̀kùn fún olólùfẹ́ mi;

Òjíá ń kán tótó ní ọwọ́ mi,

Òjíá olómi ń kán ní àwọn ìka mi,

Sára ọwọ́ ilẹ̀kùn.

 6 Mo ṣílẹ̀kùn fún olólùfẹ́ mi,

Àmọ́ olólùfẹ́ mi ti pa dà, ó ti lọ.

Àfi bíi pé kò sí ìrètí fún mi* nígbà tó lọ.*

Mo wá a, ṣùgbọ́n mi ò rí i.+

Mo pè é, àmọ́ kò dá mi lóhùn.

 7 Àwọn tó ń ṣọ́ ìlú rí mi nígbà tí wọ́n ń lọ yí ká.

Wọ́n lù mí, wọ́n ṣe mí léṣe.

Àwọn tó ń ṣọ́ ògiri ṣí ìborùn* mi kúrò lára mi.

 8 Mo mú kí ẹ búra, ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù:

Tí ẹ bá rí olólùfẹ́ mi,

Kí ẹ sọ fún un pé òjòjò ìfẹ́ ń ṣe mí.”

 9 “Kí ló mú kí olólùfẹ́ rẹ dára ju àwọn olólùfẹ́ míì lọ,

Ìwọ tó rẹwà jù nínú àwọn obìnrin?

Kí ló mú kí olólùfẹ́ rẹ dára ju àwọn olólùfẹ́ míì lọ,

Tí o fi mú ká ṣe irú ìbúra yìí?”

10 “Olólùfẹ́ mi rẹwà, ó sì mọ́ra;

Kò sí ẹni tí a lè fi í wé láàárín ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin.

11 Wúrà ni orí rẹ̀, wúrà tó dára jù.

Irun orí rẹ̀ dà bí imọ̀ ọ̀pẹ tó ń fẹ́ lẹ́lẹ́,*

Ó dúdú bí ẹyẹ ìwò.

12 Ojú rẹ̀ dà bí àwọn àdàbà tó wà létí odò,

Tí wọ́n ń wẹ̀ nínú wàrà,

Tí wọ́n wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tó kún.*

13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ dà bí ebè tí wọ́n gbin ewé tó ń ta sánsán sí,+

Òkìtì ewéko tó ń ta sánsán.

Ètè rẹ̀ dà bí òdòdó lílì, òjíá olómi+ sì ń kán tótó ní ètè rẹ̀.

14 Ọwọ́ rẹ̀ dà bí òpó wúrà, tí wọ́n fi kírísóláítì ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.

Ikùn rẹ̀ dà bí eyín erin tó ń dán, tí wọ́n fi òkúta sàfáyà bò.

15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ dà bí àwọn òpó tí wọ́n fi òkúta mábù ṣe, tó ní ìtẹ́lẹ̀ wúrà tó dára jù.

Ó rí bíi Lẹ́bánónì, kò sí ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ bí àwọn igi kédárì.+

16 Ẹnu* rẹ̀ gangan ni adùn,

Kò sóhun tí kò wuni nípa rẹ̀.+

Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù, olólùfẹ́ mi nìyí, òun lẹni tí mo nífẹ̀ẹ́.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́