Sekaráyà
2 Mo wòkè, mo sì rí ọkùnrin kan tó mú okùn ìdíwọ̀n+ dání. 2 Torí náà, mo bi í pé: “Ibo lò ń lọ?”
Ó fèsì pé: “Mo fẹ́ lọ wọn Jerúsálẹ́mù kí n lè mọ bó ṣe fẹ̀ tó àti bó ṣe gùn tó.”+
3 Wò ó! áńgẹ́lì tó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, áńgẹ́lì míì sì wá pàdé rẹ̀. 4 Ó wá sọ fún un pé: “Sáré lọ síbẹ̀ yẹn, kí o sì sọ fún ọkùnrin yẹn pé, ‘“Wọn yóò gbé inú Jerúsálẹ́mù+ bí ìgbèríko gbalasa,* nítorí gbogbo èèyàn àti ẹran ọ̀sìn tó máa wà nínú rẹ̀.”+ 5 Jèhófà kéde pé, “Èmi yóò di ògiri iná fún un yí ká,+ màá sì mú kí ògo mi wà láàárín rẹ̀.”’”+
6 Jèhófà kéde pé, “Ẹ wá! Ẹ wá! Ẹ sá kúrò ní ilẹ̀ àríwá.”+
“Torí mo ti fọ́n yín káàkiri,”*+ ni Jèhófà wí.
7 “Wá, Síónì! Sá àsálà, ìwọ tí ń gbé pẹ̀lú ọmọbìnrin Bábílónì.+ 8 Torí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí, lẹ́yìn tí a ti yìn ín lógo, ó rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tó ń kó ẹrù yín,+ pé; ‘Ẹni tó bá fọwọ́ kàn yín ń fọwọ́ kan ẹyinjú* mi.+ 9 Wọ́n á rí ìbínú mi, àwọn ìránṣẹ́ wọn yóò sì kó ẹrù wọn.’+ Ó sì dájú pé ẹ máa mọ̀ pé Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ló rán mi.
10 “Kígbe ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Síónì;+ torí mò ń bọ̀,+ èmi yóò sì máa gbé láàárín rẹ,”+ ni Jèhófà wí. 11 “Ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè yóò fara mọ́ Jèhófà ní ọjọ́ náà,+ wọ́n á sì di èèyàn mi; èmi yóò sì máa gbé láàárín yín.” Ẹ ó sì mọ̀ pé Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ló rán mi sí yín. 12 Jèhófà yóò gba Júdà bí ìpín rẹ̀ lórí ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún Jerúsálẹ́mù yàn.+ 13 Gbogbo aráyé,* ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Jèhófà torí ó ń gbé ìgbésẹ̀ láti ibi mímọ́ tó ń gbé.