Sekaráyà
10 “Ẹ bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kí òjò rọ̀ ní àsìkò ìrúwé.
Àlá tí kò ní láárí ni wọ́n ń rọ́,
Lásán sì ni wọ́n ń gbìyànjú láti tu àwọn èèyàn nínú.
Ìdí nìyẹn tí wọ́n á fi rìn gbéregbère bí àgùntàn.
Wọ́n á jìyà torí kò sí olùṣọ́ àgùntàn.
3 Inú bí mi gan-an sí àwọn olùṣọ́ àgùntàn,
Èmi yóò sì mú kí àwọn aṣáájú tó ń ni àwọn èèyàn lára* jíhìn;
Torí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ti yíjú sí agbo rẹ̀,+ sí ilé Júdà,
Ó sì mú kí wọ́n dà bí ẹṣin rẹ̀ tó gbayì tó fi ń jagun.
4 Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni olórí* ti wá,
Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni alákòóso tó ń tini lẹ́yìn* ti wá,
Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ọfà tí wọ́n fi ń jagun ti wá;
Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni gbogbo alábòójútó,* ti jáde lọ, gbogbo wọn pátá.
5 Wọn yóò dà bí àwọn jagunjagun,
Tó ń tẹ ẹrọ̀fọ̀ ojú ọ̀nà mọ́lẹ̀ lójú ogun.
6 Èmi yóò gbé ilé Júdà lékè,
Èmi yóò sì gba ilé Jósẹ́fù là.+
Màá dá wọn pa dà,
Torí èmi yóò ṣàánú wọn;+
Wọn yóò sì dà bí ẹni tí mi ò ta nù rí;+
Torí èmi ni Jèhófà Ọlọ́run wọn, màá sì dá wọn lóhùn.
7 Àwọn ti Éfúrémù yóò dà bíi jagunjagun tó lákíkanjú,
Ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bíi pé wọ́n mu wáìnì.+
Àwọn ọmọ wọn á rí èyí, inú wọn á sì dùn;
Ọkàn wọn máa yọ̀ torí Jèhófà.+
8 ‘Màá súfèé sí wọn, màá sì kó wọn jọ;
Torí màá rà wọ́n pa dà,+ wọ́n á sì pọ̀ sí i,
Wọ́n á sì máa pọ̀ sí i.
9 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo fọ́n wọn ká bí irúgbìn sáàárín àwọn èèyàn,
Wọ́n á rántí mi ní ọ̀nà jíjìn tí wọ́n wà;
Wọn á pa dà lókun, pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọ́n á sì pa dà.
10 Màá mú wọn pa dà wá láti ilẹ̀ Íjíbítì,
Màá sì kó wọn jọ láti Ásíríà;+
Màá mú wọn wá sí ilẹ̀ Gílíádì+ àti Lẹ́bánónì,
Kò sì ní sí àyè fún wọn.+
Ìgbéraga Ásíríà yóò rọlẹ̀,
Ọ̀pá àṣẹ Íjíbítì yóò sì kúrò lọ́wọ́ rẹ̀.+