ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sekaráyà 10
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sekaráyà

      • Jèhófà ni kí ẹ bẹ̀ pé kó rọ̀jò, kì í ṣe àwọn ọlọ́run èké (1, 2)

      • Jèhófà mú kí àwọn èèyàn rẹ̀ wà níṣọ̀kan (3-12)

        • Olórí tó wá láti ilé Júdà (3, 4)

Sekaráyà 10:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 11:14; Jer 14:22; 51:16; Isk 34:26; Joẹ 2:23

Sekaráyà 10:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn òrìṣà ìdílé; àwọn òrìṣà.”

  • *

    Tàbí “sọ ohun abàmì; sọ ohun àdììtú.”

Sekaráyà 10:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “òbúkọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 34:16, 17

Sekaráyà 10:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ilé ìṣọ́ igun ilé,” ó ṣàpẹẹrẹ èèyàn pàtàkì; ìjòyè.

  • *

    Ní Héb., “èèkàn,” ó ṣàpẹẹrẹ ẹni tó ń tini lẹ́yìn; alákòóso.

  • *

    Tàbí “akóniṣiṣẹ́.”

Sekaráyà 10:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 20:1
  • +Hag 2:22

Sekaráyà 10:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 3:18; Isk 37:16, 19; Ho 1:10, 11
  • +Jer 31:9, 20
  • +Jer 30:18

Sekaráyà 10:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sek 9:15
  • +Ais 66:14; Sef 3:14

Sekaráyà 10:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 44:22; 51:11

Sekaráyà 10:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 11:11
  • +Jer 50:19; Mik 7:14
  • +Ais 49:19, 20; 54:1, 2

Sekaráyà 10:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 11:15
  • +Ais 19:1; Isk 30:13

Sekaráyà 10:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 41:10; 45:24
  • +Mik 4:5

Àwọn míì

Sek. 10:1Di 11:14; Jer 14:22; 51:16; Isk 34:26; Joẹ 2:23
Sek. 10:3Isk 34:16, 17
Sek. 10:5Di 20:1
Sek. 10:5Hag 2:22
Sek. 10:6Jer 3:18; Isk 37:16, 19; Ho 1:10, 11
Sek. 10:6Jer 31:9, 20
Sek. 10:6Jer 30:18
Sek. 10:7Sek 9:15
Sek. 10:7Ais 66:14; Sef 3:14
Sek. 10:8Ais 44:22; 51:11
Sek. 10:10Ais 11:11
Sek. 10:10Jer 50:19; Mik 7:14
Sek. 10:10Ais 49:19, 20; 54:1, 2
Sek. 10:11Ais 11:15
Sek. 10:11Ais 19:1; Isk 30:13
Sek. 10:12Ais 41:10; 45:24
Sek. 10:12Mik 4:5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Sekaráyà 10:1-12

Sekaráyà

10 “Ẹ bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kí òjò rọ̀ ní àsìkò ìrúwé.

Jèhófà ló ń mú kí òjò ṣú dẹ̀dẹ̀,

Òun ló ń rọ òjò fún wọn,+

Òun ló sì ń fún gbogbo èèyàn ní ewéko.

 2 Torí àwọn ère tẹ́ráfímù* ti sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn;*

Àwọn woṣẹ́woṣẹ́ sì ti rí ìran èké.

Àlá tí kò ní láárí ni wọ́n ń rọ́,

Lásán sì ni wọ́n ń gbìyànjú láti tu àwọn èèyàn nínú.

Ìdí nìyẹn tí wọ́n á fi rìn gbéregbère bí àgùntàn.

Wọ́n á jìyà torí kò sí olùṣọ́ àgùntàn.

 3 Inú bí mi gan-an sí àwọn olùṣọ́ àgùntàn,

Èmi yóò sì mú kí àwọn aṣáájú tó ń ni àwọn èèyàn lára* jíhìn;

Torí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ti yíjú sí agbo rẹ̀,+ sí ilé Júdà,

Ó sì mú kí wọ́n dà bí ẹṣin rẹ̀ tó gbayì tó fi ń jagun.

 4 Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni olórí* ti wá,

Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni alákòóso tó ń tini lẹ́yìn* ti wá,

Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ọfà tí wọ́n fi ń jagun ti wá;

Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni gbogbo alábòójútó,* ti jáde lọ, gbogbo wọn pátá.

 5 Wọn yóò dà bí àwọn jagunjagun,

Tó ń tẹ ẹrọ̀fọ̀ ojú ọ̀nà mọ́lẹ̀ lójú ogun.

Wọ́n á jagun torí Jèhófà wà pẹ̀lú wọn;+

Ojú yóò sì ti àwọn tó ń gun ẹṣin.+

 6 Èmi yóò gbé ilé Júdà lékè,

Èmi yóò sì gba ilé Jósẹ́fù là.+

Màá dá wọn pa dà,

Torí èmi yóò ṣàánú wọn;+

Wọn yóò sì dà bí ẹni tí mi ò ta nù rí;+

Torí èmi ni Jèhófà Ọlọ́run wọn, màá sì dá wọn lóhùn.

 7 Àwọn ti Éfúrémù yóò dà bíi jagunjagun tó lákíkanjú,

Ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bíi pé wọ́n mu wáìnì.+

Àwọn ọmọ wọn á rí èyí, inú wọn á sì dùn;

Ọkàn wọn máa yọ̀ torí Jèhófà.+

 8 ‘Màá súfèé sí wọn, màá sì kó wọn jọ;

Torí màá rà wọ́n pa dà,+ wọ́n á sì pọ̀ sí i,

Wọ́n á sì máa pọ̀ sí i.

 9 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo fọ́n wọn ká bí irúgbìn sáàárín àwọn èèyàn,

Wọ́n á rántí mi ní ọ̀nà jíjìn tí wọ́n wà;

Wọn á pa dà lókun, pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọ́n á sì pa dà.

10 Màá mú wọn pa dà wá láti ilẹ̀ Íjíbítì,

Màá sì kó wọn jọ láti Ásíríà;+

Màá mú wọn wá sí ilẹ̀ Gílíádì+ àti Lẹ́bánónì,

Kò sì ní sí àyè fún wọn.+

11 Yóò la òkun kọjá pẹ̀lú wàhálà;

Yóò sì pa ìgbì òkun lẹ́nu mọ́;+

Gbogbo ibú Náílì yóò gbẹ táútáú.

Ìgbéraga Ásíríà yóò rọlẹ̀,

Ọ̀pá àṣẹ Íjíbítì yóò sì kúrò lọ́wọ́ rẹ̀.+

12 Èmi, Jèhófà, yóò gbé wọn lékè,+

Wọn yóò sì máa rìn ní orúkọ mi,’+ ni Jèhófà wí.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́