ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nọ́ńbà 36
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Nọ́ńbà

      • Òfin nípa ẹni tí àwọn obìnrin tó ní ogún máa fẹ́ (1-13)

Nọ́ńbà 36:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 26:29

Nọ́ńbà 36:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 26:55; 33:54
  • +Nọ 27:1-7

Nọ́ńbà 36:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:10

Nọ́ńbà 36:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 23:22

Nọ́ńbà 36:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 36:6

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/15/2008, ojú ìwé 4-5

Nọ́ńbà 36:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 27:1

Nọ́ńbà 36:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 26:3; 33:50; 35:1

Àwọn míì

Nọ́ń. 36:1Nọ 26:29
Nọ́ń. 36:2Nọ 26:55; 33:54
Nọ́ń. 36:2Nọ 27:1-7
Nọ́ń. 36:4Le 25:10
Nọ́ń. 36:81Kr 23:22
Nọ́ń. 36:10Nọ 36:6
Nọ́ń. 36:11Nọ 27:1
Nọ́ń. 36:13Nọ 26:3; 33:50; 35:1
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Nọ́ńbà 36:1-13

Nọ́ńbà

36 Àwọn olórí ìdílé àwọn àtọmọdọ́mọ Gílíádì ọmọ Mákírù+ ọmọ Mánásè láti ìdílé àwọn ọmọ Jósẹ́fù wá sọ́dọ̀ Mósè àti àwọn ìjòyè, àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, láti bá wọn sọ̀rọ̀. 2 Wọ́n sọ pé: “Jèhófà pàṣẹ fún olúwa mi pé kó fi kèké+ pín ilẹ̀ náà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kí wọ́n lè jogún rẹ̀; Jèhófà sì pàṣẹ fún olúwa mi pé kó fún àwọn ọmọbìnrin + Sélóféhádì arákùnrin wa ní ogún bàbá wọn. 3 Àmọ́ tí wọ́n bá lọ́kọ látinú ẹ̀yà míì ní Ísírẹ́lì, ogún àwọn obìnrin náà máa kúrò nínú ogún àwọn bàbá wa, ó sì máa kún ti ogún ẹ̀yà tí wọ́n máa fẹ́ wọn sí, kò wá ní sí lára ogún tí wọ́n fi kèké pín fún wa. 4 Tí àkókò Júbílì+ bá wá tó fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ogún àwọn obìnrin náà máa kún ti ogún ẹ̀yà tí wọ́n máa fẹ́ wọn sí, ogún wọn ò sì ní sí lára ogún ẹ̀yà àwọn bàbá wa mọ́.”

5 Mósè wá pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ pé: “Òótọ́ ni ohun tí ẹ̀yà àwọn ọmọ Jósẹ́fù ń sọ. 6 Ohun tí Jèhófà sọ nípa àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì ni pé: ‘Wọ́n lè fẹ́ ẹni tó bá wù wọ́n. Àmọ́, inú ìdílé tó wá látinú ẹ̀yà bàbá wọn ni kí wọ́n ti fẹ́ ẹ. 7 Ogún èyíkéyìí tó jẹ́ ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò gbọ́dọ̀ ti ọwọ́ ẹ̀yà kan bọ́ sí òmíràn, torí kò yẹ kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ogún ẹ̀yà baba ńlá wọn sílẹ̀. 8 Kí ọmọbìnrin èyíkéyìí tó bá ní ogún láàárín ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fẹ́ ọ̀kan nínú àtọmọdọ́mọ ẹ̀yà+ bàbá rẹ̀, kí ogún baba ńlá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lè máa wà ní ìkáwọ́ wọn. 9 Ogún èyíkéyìí kò gbọ́dọ̀ ti ọwọ́ ẹ̀yà kan bọ́ sí òmíràn, torí kò yẹ kí àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì fi ogún wọn sílẹ̀.’”

10 Àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì ṣe ohun tí Jèhófà pa láṣẹ fún Mósè+ gẹ́lẹ́. 11 Torí náà, Málà, Tírísà, Hógílà, Mílíkà àti Nóà, àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì,+ fẹ́ ọkọ láàárín àwọn ọmọ àwọn arákùnrin bàbá wọn. 12 Wọ́n lọ́kọ nínú ìdílé Mánásè ọmọ Jósẹ́fù, kí ogún wọn má bàa kúrò nínú ẹ̀yà ìdílé bàbá wọn.

13 Èyí ni àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà ìdájọ́ tí Jèhófà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípasẹ̀ Mósè ní aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Móábù, lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì ní Jẹ́ríkò.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́