ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 11
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Sámúẹ́lì

      • Dáfídì àti Bátí-ṣébà ṣe àgbèrè (1-13)

      • Dáfídì ṣètò pé kí wọ́n pa Ùráyà (14-25)

      • Dáfídì fi Bátí-ṣébà ṣe aya (26, 27)

2 Sámúẹ́lì 11:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, nígbà tí ọdún yí po.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:26
  • +1Kr 20:1

2 Sámúẹ́lì 11:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ní ọjọ́rọ̀.”

  • *

    Tàbí “ààfin.”

2 Sámúẹ́lì 11:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:24; 1Ọb 1:11
  • +1Kr 3:5, 9
  • +2Sa 23:8, 39; 1Ọb 15:5
  • +Jẹ 10:15; Di 20:17

2 Sámúẹ́lì 11:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ àìmọ́ ti nǹkan oṣù.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:14, 17
  • +Le 18:20; 20:10; Owe 6:32; Heb 13:4
  • +Le 12:2; 15:19; 18:19

2 Sámúẹ́lì 11:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wẹ ẹsẹ̀ rẹ.”

  • *

    Tàbí “ìpín ọba,” ìyẹn, ohun tí ẹni tó gbàlejò fi ránṣẹ́ sí àlejò rẹ̀ pàtàkì.

2 Sámúẹ́lì 11:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ọkàn rẹ sì wà láàyè.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 6:17; 7:2
  • +Le 15:16; 1Sa 21:5

2 Sámúẹ́lì 11:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 51:14; Owe 3:29

2 Sámúẹ́lì 11:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:9

2 Sámúẹ́lì 11:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Òun ló ń jẹ́ Jerubáálì tàbí Gídíónì (Ond 6:32; 7:1).

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 9:50-53
  • +Ond 6:32; 7:1

2 Sámúẹ́lì 11:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 11:17

2 Sámúẹ́lì 11:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:26

2 Sámúẹ́lì 11:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “burú lójú Jèhófà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 5:13; 12:9
  • +Jẹ 39:7-9; 1Ọb 15:5; Sm 5:6; 11:4; Heb 13:4

Àwọn míì

2 Sám. 11:12Sa 12:26
2 Sám. 11:11Kr 20:1
2 Sám. 11:32Sa 12:24; 1Ọb 1:11
2 Sám. 11:31Kr 3:5, 9
2 Sám. 11:32Sa 23:8, 39; 1Ọb 15:5
2 Sám. 11:3Jẹ 10:15; Di 20:17
2 Sám. 11:4Ẹk 20:14, 17
2 Sám. 11:4Le 18:20; 20:10; Owe 6:32; Heb 13:4
2 Sám. 11:4Le 12:2; 15:19; 18:19
2 Sám. 11:112Sa 6:17; 7:2
2 Sám. 11:11Le 15:16; 1Sa 21:5
2 Sám. 11:15Sm 51:14; Owe 3:29
2 Sám. 11:172Sa 12:9
2 Sám. 11:21Ond 9:50-53
2 Sám. 11:21Ond 6:32; 7:1
2 Sám. 11:242Sa 11:17
2 Sám. 11:252Sa 12:26
2 Sám. 11:272Sa 5:13; 12:9
2 Sám. 11:27Jẹ 39:7-9; 1Ọb 15:5; Sm 5:6; 11:4; Heb 13:4
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Sámúẹ́lì 11:1-27

Sámúẹ́lì Kejì

11 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún,* lákòókò tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dáfídì rán Jóábù àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì pé kí wọ́n lọ pa àwọn ọmọ Ámónì run, wọ́n sì dó ti Rábà,+ àmọ́ Dáfídì dúró sí Jerúsálẹ́mù.+

2 Nírọ̀lẹ́ ọjọ́* kan, Dáfídì dìde lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé* ọba. Láti orí òrùlé náà, ó rí obìnrin kan tó ń wẹ̀, obìnrin náà sì rẹwà gan-an. 3 Dáfídì rán ẹnì kan láti lọ wádìí nípa obìnrin náà, ẹni náà sì wá jábọ̀ pé: “Ṣebí Bátí-ṣébà+ ọmọ Élíámù+ ìyàwó Ùráyà+ ọmọ Hétì ni.”+ 4 Lẹ́yìn náà, Dáfídì ní kí àwọn òjíṣẹ́ lọ mú un wá.+ Torí náà, ó wọlé wá bá a, ó sì bá a sùn.+ (Èyí ṣẹlẹ̀ nígbà tí obìnrin náà ń wẹ ara rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ohun àìmọ́*+ rẹ̀.) Lẹ́yìn náà, ó pa dà sílé rẹ̀.

5 Obìnrin náà lóyún, ó sì ránṣẹ́ sí Dáfídì pé: “Mo ti lóyún.” 6 Ni Dáfídì bá ránṣẹ́ sí Jóábù pé: “Rán Ùráyà ọmọ Hétì sí mi.” Torí náà, Jóábù rán Ùráyà sí Dáfídì. 7 Nígbà tí Ùráyà dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dáfídì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ bí Jóábù ṣe ń ṣe sí àti bí àwọn ọmọ ogun ṣe ń ṣe sí, ó sì tún béèrè bí ogun náà ṣe ń lọ sí. 8 Dáfídì wá sọ fún Ùráyà pé: “Lọ sí ilé rẹ, kí o lọ sinmi.”* Nígbà tí Ùráyà kúrò ní ilé ọba, ọba fi ẹ̀bùn* ránṣẹ́ sí i. 9 Àmọ́, Ùráyà sùn sí ẹnu ọ̀nà ilé ọba pẹ̀lú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì lọ sí ilé rẹ̀. 10 Torí náà, wọ́n sọ fún Dáfídì pé: “Ùráyà kò lọ sí ilé rẹ̀ o.” Dáfídì wá sọ fún Ùráyà pé: “Ṣebí o ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ìrìn àjò ni? Kí ló dé tí o ò lọ sí ilé rẹ?” 11 Ùráyà dá Dáfídì lóhùn pé: “Àpótí  + àti gbogbo ọmọ ogun Ísírẹ́lì àti ti Júdà ń gbé lábẹ́ àtíbàbà, olúwa mi Jóábù àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi sì pàgọ́ sórí pápá. Ṣé ó wá yẹ kí n lọ sínú ilé mi láti jẹ àti láti mu àti láti bá ìyàwó mi sùn?+ Bí o ti wà láàyè, tí o sì ń mí,* mi ò jẹ́ ṣe nǹkan yìí!”

12 Dáfídì wá sọ fún Ùráyà pé: “Tún dúró síbí lónìí, tó bá sì di ọ̀la, màá jẹ́ kí o máa lọ.” Nítorí náà, Ùráyà dúró sí Jerúsálẹ́mù ní ọjọ́ yẹn àti ní ọjọ́ kejì. 13 Lẹ́yìn náà, Dáfídì ní kí wọ́n lọ pè é wá, kí ó wá bá òun jẹun, kí ó sì mu, ni ó bá rọ ọ́ yó. Àmọ́ nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, ó lọ sùn sórí ibùsùn rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì lọ sí ilé rẹ̀. 14 Láàárọ̀ ọjọ́ kejì, Dáfídì kọ lẹ́tà kan sí Jóábù, ó sì fi rán Ùráyà. 15 Ó kọ ọ́ sínú lẹ́tà náà pé: “Ẹ fi Ùráyà síwájú níbi tí ogun ti le jù lọ. Lẹ́yìn náà kí ẹ pa dà lẹ́yìn rẹ̀, kí wọ́n lè mú un balẹ̀, kí ó sì kú.”+

16 Jóábù ti ń ṣọ́ ìlú náà lójú méjèèjì, ó wá fi Ùráyà sí ibi tí ó mọ̀ pé àwọn jagunjagun tó lákíkanjú wà. 17 Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà jáde wá bá Jóábù jà, àwọn kan lára ìránṣẹ́ Dáfídì kú, Ùráyà ọmọ Hétì sì wà lára àwọn tó kú.+ 18 Jóábù wá ránṣẹ́ sí Dáfídì láti ròyìn gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ lójú ogun fún un. 19 Ó sọ fún òjíṣẹ́ náà pé: “Tí o bá ti ròyìn gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ lójú ogun fún ọba tán, 20 ọba lè bínú, kí ó sọ fún ọ pé, ‘Kí ló dé tí ẹ fi sún mọ́ ìlú náà tó bẹ́ẹ̀ láti jà? Ṣé ẹ ò mọ̀ pé wọ́n máa ta ọfà láti orí ògiri ni? 21 Àbí, ta ló pa Ábímélékì+ ọmọ Jerubéṣétì?*+ Ṣé kì í ṣe obìnrin ló ju ọlọ lù ú láti orí ògiri tí ó fi kú ní Tébésì? Kí ló dé tí ẹ fi sún mọ́ ògiri náà tó bẹ́ẹ̀?’ Kí o wá sọ pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ Ùráyà ọmọ Hétì náà kú.’”

22 Nítorí náà, òjíṣẹ́ náà lọ sọ́dọ̀ Dáfídì, ó sì sọ gbogbo ohun tí Jóábù ní kó sọ. 23 Ìgbà náà ni òjíṣẹ́ náà sọ fún Dáfídì pé: “Àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n jáde láti bá wa jà ní pápá; àmọ́ a lé wọn pa dà síbi àtiwọ ẹnubodè ìlú. 24 Àwọn tafàtafà sì ń ta àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ́fà láti orí ògiri, àwọn kan lára ìránṣẹ́ ọba kú; ìránṣẹ́ rẹ Ùráyà ọmọ Hétì náà sì kú.”+ 25 Ni Dáfídì bá sọ fún òjíṣẹ́ náà pé: “Sọ fún Jóábù pé: ‘Má ṣe jẹ́ kí ọ̀ràn yìí dà ọ́ láàmú, kò sẹ́ni tí idà ò lè pa lójú ogun. Túbọ̀ múra sí ìjà tí ò ń bá ìlú náà jà, kí o sì ṣẹ́gun rẹ̀.’+ Kí o bá mi fún Jóábù ní ìṣírí.”

26 Nígbà tí ìyàwó Ùráyà gbọ́ pé Ùráyà ọkọ òun ti kú, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣọ̀fọ̀ ọkọ rẹ̀. 27 Gbàrà tí àkókò ọ̀fọ̀ náà parí, Dáfídì ránṣẹ́ sí i, ó mú un wá sí ilé rẹ̀, ó di ìyàwó rẹ̀,+ ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un. Àmọ́ ohun tí Dáfídì ṣe yìí bí Jèhófà nínú* gan-an.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́