ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 10/07 ojú ìwé 22
  • Jẹ́ Kí Ilé Rẹ Jẹ́ Ilé Aláyọ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jẹ́ Kí Ilé Rẹ Jẹ́ Ilé Aláyọ̀
  • Jí!—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ̀yin Òbí, Ẹ Kọ́ Àwọn Ọmọ Yín Kí Wọ́n Lè Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
  • Gbígbé Ìdílé Tó Dúró Sán-ún Nípa Tẹ̀mí Ró
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Béèyàn Ṣe Lè ní Ojúlówó Ìfẹ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Ẹ Kọ́ Àwọn Ọmọ Yín Láti Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
Àwọn Míì
Jí!—2007
g 10/07 ojú ìwé 22

Ọ̀nà 2

Jẹ́ Kí Ilé Rẹ Jẹ́ Ilé Aláyọ̀

Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì? Ó yẹ ká fẹ́ràn àwọn ọmọdé, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ wọn ò ní ya ọmọ rere. Láàárín ọdún 1950 sí ọdún 1959, onímọ̀ nípa ẹ̀dá èèyàn, Ọ̀gbẹ́ni M. F. Ashley Montagu kọ̀wé pé: “Kọ́mọ bàa lè yàn kó yanjú, àfi ká máa fìfẹ́ hàn sí i; ó sì fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé láìsí ìfẹ́ ńṣe lọmọ á rán, pàápàá láàárín ọdún mẹ́fà tó bá kọ́kọ́ lò láyé.” Bí Ọ̀gbẹ́ni Montagu ṣe sọ lọ̀rọ̀ náà ṣe rí lójú àwọn ògbógi tó ń ṣèwádìí nípa ọ̀ràn ọmọ títọ́ lóde òní. Ohun tí ọ̀gbẹ́ni Montagu sì fi parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ ni pé “báwọn ọmọ ò bá rẹ́ni fìfẹ́ hàn sí wọn bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ, ńṣe ni wọ́n máa ń ya ọmọkọ́mọ.”

Ìṣòro tó wà ńbẹ̀: Ńṣe layé bó o bá a o pa á, bó ò bá a o bù ú lẹ́sẹ̀, táwọn èèyàn ti ya onímọ̀-tara-ẹni nìkan tá à ń gbé yìí ń mú kí àìsí ìṣọ̀kan túbọ̀ máa wà láàárín ọkọ, aya àtàwọn ọmọ. (2 Tímótì 3:1-5) Àwọn lọ́kọláya sì tún ti lè rí i pé ńṣe ni ìṣòro tó wà nínú ìgbéyàwó máa ń ga sí i bí ọ̀rọ̀ gbígbọ́ bùkátà àwọn ọmọ àti gbígba tiwọn rò bá wọ̀ ọ́. Bí àpẹẹrẹ, bó bá jẹ́ pé tọkọtaya ti níṣòro àtimáa bára wọn sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀, ńṣe lọ̀rọ̀ wọn á túbọ̀ máa burú sí i bó bá tún wá lọ jẹ́ pé èrò wọn kì í ṣọ̀kan lórí ọ̀nà tó yẹ kí wọ́n máa gbà bá ọmọ wí àti ọ̀nà tó yẹ kí wọ́n máa gbà gbóríyìn fáwọn ọmọ.

Ohun tó lè ràn yín lọ́wọ́: Ẹ jùmọ̀ máa ṣe nǹkan pọ̀ déédéé gẹ́gẹ́ bí ìdílé. Ó tún yẹ káwọn tọkọtaya máa wá àkókò tí wọ́n á fi jọ máa finú konú. (Ámósì 3:3) Ẹ máa lo àkókò tó bá ṣẹ́ kù fún yín lọ́nà rere lẹ́yìn táwọn ọmọ bá ti lọ sùn. Ẹ má ṣe jẹ́ kí tẹlifíṣọ̀n gba àkókò ṣíṣeyebíye yẹn mọ́ ọn yín lọ́wọ́. Ẹ máa fìfẹ́ hàn síra yín déédéé kẹ́ ẹ má bàa ṣá lójú ara yín. (Òwe 25:11; Orin Sólómọ́nì 4:7-10) Dípò tẹ́ ẹ ó fi máa “wá àléébù” ara yín ní gbogbo ìgbà, ṣe ni kẹ́ ẹ máa wá ọ̀nà tẹ́ ẹ ó fi máa gbóríyìn fúnra yín lójoojúmọ́.—Sáàmù 103:9, 10; Òwe 31:28.

Máa sọ fáwọn ọmọ ẹ pó o fẹ́ràn wọn. Jèhófà Ọlọ́run fi àpẹẹrẹ èyí lélẹ̀ fáwọn òbí nípa sísọ fún Jésù tó jẹ́ ọmọ rẹ̀ pé òun fẹ́ràn rẹ̀ gan-an. (Mátíù 3:17; 17:5) Baálé ilé kan tó ń jẹ́ Fleck, tó ń gbé ní Austria, sọ pé: “Mo ti wá rí i pé bí òdòdó làwọn ọmọdé rí. Bí òdòdó ṣe máa ń tẹ̀ síbi tí ìtànṣán oòrùn bá wà kó lè gba ìmọ́lẹ̀ àti ooru sára, bẹ́ẹ̀ náà làwọn ọmọ máa ń fẹ́ káwọn òbí fìfẹ́ hàn sáwọn, kí wọ́n sì tún máa mú un dá àwọn lójú pé àwọn ò kóyán àwọn kéré nínú ìdílé.”

Yálà o ti ṣègbéyàwó tàbí o jẹ́ òbí anìkàntọ́mọ, bó o bá jẹ́ káwọn tó wà nínú ìdílé ẹ nífẹ̀ẹ́ ara wọn kí wọ́n sì tún nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run, wàá rí i pé ìyàtọ̀ á wà nínú ìdílé ẹ.

Àmọ́, kí tiẹ̀ lọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ nípa bó o ṣe lè máa lo àṣẹ rẹ gẹ́gẹ́ bí òbí nínú ilé?

[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 22]

“Ìfẹ́ . . . jẹ́ ìdè ìrẹ́pọ̀ pípé.”—Kólósè 3:14

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́