September
Monday, September 1
Ojúmọ́ kan máa mọ́ wa láti ibi gíga.—Lúùkù 1:78.
Ọlọ́run fún Jésù lágbára láti yanjú ìṣòro aráyé. Àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe fi hàn pé ó lágbára láti yanjú àwọn ìṣòro tá ò lè yanjú fúnra wa. Bí àpẹẹrẹ, ó lágbára láti gbà wá lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tá a jogún àtàwọn nǹkan tí ẹ̀ṣẹ̀ náà fà irú bí àìsàn àti ikú. (Mát. 9:1-6; Róòmù 5:12, 18, 19) Àwọn iṣẹ́ ìyanu tó ṣe fi hàn pé ó lè wo “onírúurú” àìsàn, ó sì lè jí òkú dìde. (Mát. 4:23; Jòh. 11:43, 44) Bákan náà, ó lágbára láti dáwọ́ ìjì líle dúró, ó sì lágbára láti gba àwọn èèyàn sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀mí burúkú. (Máàkù 4:37-39; Lúùkù 8:2) Àwọn nǹkan yìí jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà ti fún Ọmọ ẹ̀ lágbára láti yanjú àwọn ìṣòro wa! Ó dá wa lójú háún-háún pé Ọlọ́run máa ṣe àwọn ohun rere tó ṣèlérí nínú Ìjọba rẹ̀. Àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé tó bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé, ó máa ṣe jù bẹ́ẹ̀ lọ torí pé òun ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run. w23.04 3 ¶5-7
Tuesday, September 2
Ẹ̀mí ń wá inú ohun gbogbo, títí kan àwọn ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run.—1 Kọ́r. 2:10.
Táwọn ará tó wà nínú ìjọ tó o wà bá pọ̀, ó lè má rọrùn fún ẹ láti dáhùn. Torí náà, má jẹ́ kó sú ẹ láti nawọ́ kó o lè dáhùn. Múra ìdáhùn tó pọ̀. Tí wọn ò bá pè ẹ́ níbẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ náà, wọ́n ṣì lè pè ẹ́ bẹ́ ẹ ṣe ń bá ẹ̀kọ́ náà lọ. Tó o bá ń múra ìkẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́, ronú nípa bí ìpínrọ̀ kọ̀ọ̀kan ṣe ṣàlàyé àkòrí ẹ̀kọ́ náà. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, wàá lè dáhùn lọ́nà tó máa gbé àwọn ará ró nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ náà. Yàtọ̀ síyẹn, o lè múra láti dáhùn àwọn ẹ̀kọ́ Bíbélì tó jinlẹ̀ tó lè nira fáwọn ará láti ṣàlàyé. Kí nìdí tó fi yẹ kó o ṣe bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé àwọn tó máa nawọ́ láti dáhùn apá yìí kì í pọ̀. Ká sọ pé o ṣì rí i pé wọn kì í pè ẹ́ ńkọ́? Lọ bá ẹni tó ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà kí ìpàdé tó bẹ̀rẹ̀, kó o sì sọ ìpínrọ̀ tó o fẹ́ dáhùn fún un. w23.04 21-22 ¶9-10
Wednesday, September 3
Jósẹ́fù . . . ṣe ohun tí áńgẹ́lì Jèhófà ní kó ṣe, ó mú ìyàwó rẹ̀ lọ sílé.—Mát. 1:24.
Ìgbà gbogbo ni Jósẹ́fù máa ń fi ìmọ̀ràn Jèhófà sílò, ìyẹn ló sì mú kó jẹ́ ọkọ rere. Ó kéré tán, ẹ̀ẹ̀mẹta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni Jèhófà sọ ohun tó máa ṣe nípa ìdílé ẹ̀ fún un. Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ló sì máa ń gbé ìgbésẹ̀ kódà nígbà tó ní láti ṣe àwọn àyípadà tó le gan-an. (Mát. 1:20; 2:13-15, 19-21) Torí pé Jósẹ́fù ṣe ohun tí Jèhófà sọ, ó dáàbò bo Màríà, ó ràn án lọ́wọ́, ó sì pèsè àwọn nǹkan tó nílò. Ẹ wo bí àwọn nǹkan tí Jósẹ́fù ṣe yẹn ṣe máa mú kí Màríà túbọ̀ nífẹ̀ẹ́ ẹ̀, kó sì bọ̀wọ̀ fún un! Ẹ̀yin ọkọ, ẹ lè kẹ́kọ̀ọ́ lára Jósẹ́fù tẹ́ ẹ bá ń tẹ̀ lé àwọn ìmọ̀ràn Bíbélì lórí bẹ́ ẹ ṣe máa bójú tó ìdílé yín. Tó o bá ń fi ìmọ̀ràn yìí sílò, tó bá tiẹ̀ máa gba pé kó o ṣe àwọn àyípadà kan, wàá fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ ìyàwó ẹ, okùn ìfẹ́ yín á sì máa lágbára sí i. Arábìnrin kan láti Vanuatu tó ti ṣègbéyàwó ní ohun tó lé lógún (20) ọdún sọ pé: “Gbogbo ìgbà tí ọkọ mi bá ní kí Jèhófà tọ́ òun sọ́nà, tó sì ṣe ohun tí Jèhófà sọ ni mo túbọ̀ máa ń bọ̀wọ̀ fún un. Ọkàn mi máa ń balẹ̀, mo sì máa ń fọkàn tán an pé ìpinnu tó dáa ló máa ṣe.” w23.05 21 ¶5
Thursday, September 4
Ọ̀nà kan sì máa wà níbẹ̀, àní, ọ̀nà tí à ń pè ní Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́.—Àìsá. 35:8.
Àwọn Júù tó pa dà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn gbọ́dọ̀ jẹ́ “èèyàn mímọ́” lójú Ọlọ́run. (Diu. 7:6) Àmọ́ ìyẹn ò túmọ̀ sí pé wọn ò ní ṣe àyípadà kankan, kí wọ́n lè ṣe ohun tí Jèhófà fẹ́. Ìlú Bábílónì ni wọ́n bí ọ̀pọ̀ lára àwọn Júù yẹn sí, ọ̀nà táwọn ará Bábílónì sì ń gbà ronú àti bí wọ́n ṣe ń ṣe nǹkan ti mọ́ wọn lára. Nígbà táwọn kan lára àwọn Júù kọ́kọ́ pa dà sí Ísírẹ́lì, ó ya Gómìnà Nehemáyà lẹ́nu gan-an pé àwọn ọmọ táwọn Júù yẹn bí sí Ísírẹ́lì ò lè sọ èdè Júù. (Diu. 6:6, 7; Neh. 13:23, 24) Báwo làwọn ọmọ yẹn ṣe máa nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tí wọ́n á sì máa sìn ín tí wọn ò bá gbọ́ èdè Hébérù, ìyẹn èdè tí wọ́n fi kọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run? (Ẹ́sírà 10:3, 44) Torí náà, ó hàn gbangba pé àwọn Júù yẹn gbọ́dọ̀ ṣe àwọn àyípadà kan, ìyẹn sì máa rọrùn torí ilẹ̀ Ísírẹ́lì ni wọ́n wà níbi tí ìjọsìn mímọ́ ti ń pa dà bọ̀ sípò.—Neh. 8:8, 9. w23.05 15 ¶6-7
Friday, September 5
Jèhófà ń gbé gbogbo àwọn tó ti fẹ́ ṣubú ró, ó sì ń gbé gbogbo àwọn tó dorí kodò dìde.—Sm. 145:14.
Ó bani nínú jẹ́ pé kò sí bá a ṣe ṣiṣẹ́ kára tó tàbí bá a ṣe kó ara wa níjàánu tó, àwọn nǹkan kan ṣì lè mú kọ́wọ́ wa má tètè tẹ àfojúsùn wa. Bí àpẹẹrẹ, “ìgbà àti èèṣì” lè má jẹ́ kọ́wọ́ wa tẹ ohun tá à ń lé. (Oníw. 9:11) Yàtọ̀ síyẹn, ìṣòro lè mú ká rẹ̀wẹ̀sì, ká má sì lókun mọ́. (Òwe 24:10) Torí pé aláìpé ni wá, a lè máa ṣe ohun tí ò ní jẹ́ kọ́wọ́ wa tẹ ohun tá à ń lé. (Róòmù 7:23) Gbogbo nǹkan sì lè tojú sú wa. (Mát. 26:43) Torí náà, kí ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti borí àwọn ìṣòro yìí? Máa rántí pé tóhun kan ò bá jẹ́ kọ́wọ́ ẹ tètè tẹ nǹkan tó ò ń lé, ìyẹn ò túmọ̀ sí pé kó o pa nǹkan náà tì. Bíbélì sọ pé ìṣòro lè dé bá wa léraléra. Àmọ́, ó tún sọ pé Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ láti borí àwọn ìṣòro náà. Ó dájú pé tó o bá ń ṣiṣẹ́ kára kọ́wọ́ ẹ lè tẹ àfojúsùn ẹ bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò rọrùn, ìyẹn á jẹ́ kí Jèhófà mọ̀ pé o fẹ́ ṣohun tóun fẹ́. Wo bí inú Jèhófà ṣe máa dùn tó pé o ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe kọ́wọ́ ẹ lè tẹ ohun tó ò ń lé! w23.05 30 ¶14-15
Saturday, September 6
Ẹ jẹ́ àpẹẹrẹ fún agbo.—1 Pét. 5:3.
Tí ọ̀dọ́ kan bá ṣiṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà, á jẹ́ kó mọ bó ṣe lè bá onírúurú èèyàn ṣiṣẹ́. Yàtọ̀ síyẹn, á jẹ́ kó mọ bá a ṣe ń ṣówó ná. (Fílí. 4:11-13) Tó o bá fẹ́ ṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún, iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà olùrànlọ́wọ́ lo máa kọ́kọ́ fi bẹ̀rẹ̀, ìyẹn sì máa jẹ́ kó rọrùn fún ẹ láti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà déédéé. Tó o bá ṣiṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà, á jẹ́ kó o láǹfààní láti ṣiṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún míì. Bí àpẹẹrẹ, o lè di ọ̀kan lára àwọn tó ń kọ́lé ètò Ọlọ́run tàbí kó o máa sìn ní Bẹ́tẹ́lì. Ó yẹ káwọn arákùnrin máa ṣiṣẹ́ kára kí wọ́n lè kúnjú ìwọ̀n láti di alàgbà, á sì jẹ́ kí wọ́n lè sin àwọn ará nínú ìjọ. Bíbélì sọ pé táwọn arákùnrin bá ń ṣiṣẹ́ kára láti di alábòójútó, ‘iṣẹ́ rere ni wọ́n fẹ́ ṣe.’ (1 Tím. 3:1) Ohun àkọ́kọ́ ni pé kó kúnjú ìwọ̀n láti di ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́. Onírúurú ọ̀nà làwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ ń gbà ran àwọn alàgbà lọ́wọ́. Torí pé àwọn alàgbà àtàwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ nírẹ̀lẹ̀, wọ́n ń ran àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin lọ́wọ́, wọ́n sì ń fìtara wàásù pẹ̀lú wọn. w23.12 28 ¶14-16
Sunday, September 7
Nígbà tó ṣì jẹ́ ọ̀dọ́kùnrin, ó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Ọlọ́run Dáfídì baba ńlá rẹ̀.—2 Kíró. 34:3.
Ọ̀dọ́ ni Ọba Jòsáyà nígbà tó bẹ̀rẹ̀ sí í wá Jèhófà. Ó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, kó sì máa ṣohun tó fẹ́. Àmọ́ nǹkan ò rọrùn fún ọba tó jẹ́ ọ̀dọ́ yìí. Nígbà yẹn, ìjọsìn èké lọ̀pọ̀ èèyàn ń ṣe. Torí náà, ó di dandan pé kí Jòsáyà fìgboyà gbèjà ìjọsìn tòótọ́, ohun tó sì ṣe gan-an nìyẹn. Kódà, kí Jòsáyà tó pé ọmọ ogún (20) ọdún ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìjọsìn èké kúrò lórílẹ̀-èdè náà. (2 Kíró. 34:1, 2) Tó o bá jẹ́ ọ̀dọ́, o lè fara wé Jòsáyà tó o bá ń wá Jèhófà, tó o sì ń fàwọn ànímọ́ ẹ̀ ṣèwà hù. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, á wù ẹ́ láti ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà. Kí nìyẹn máa mú kó o ṣe lójoojúmọ́? Arákùnrin Luke tó ṣèrìbọmi nígbà tó wà lọ́mọ ọdún mẹ́rìnlá (14) sọ pé: “Àtìgbà tí mo ti ya ara mi sí mímọ́ ni mo ti pinnu pé ìfẹ́ Jèhófà ló máa gbawájú láyé mi, màá sì máa múnú ẹ̀ dùn.” (Máàkù 12:30) Tíwọ náà bá pinnu pé ohun tó o máa ṣe nìyẹn, wàá láyọ̀! w23.09 11 ¶12-13
Monday, September 8
Ẹ máa bọ̀wọ̀ fún àwọn tó ń ṣiṣẹ́ kára láàárín yín, tí wọ́n ń ṣe àbójútó yín nínú Olúwa.—1 Tẹs. 5:12.
Kò tíì pé ọdún kan tí wọ́n dá ìjọ Tẹsalóníkà sílẹ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ lẹ́tà rẹ̀ sí wọn. Torí náà, àwọn alábòójútó tí wọ́n yàn síbẹ̀ lè má fi bẹ́ẹ̀ nírìírí, wọ́n sì lè ṣe àwọn àṣìṣe kan. Síbẹ̀, àwọn ará ìjọ náà ń bọ̀wọ̀ fún wọn. Bí ìpọ́njú ńlá ṣe ń sún mọ́lé, ó máa gba pé ká túbọ̀ máa ṣe ohun táwọn alàgbà ìjọ wa bá sọ fún wa ju bá a ṣe ń ṣe lọ báyìí. Ìdí ni pé ó lè má ṣeé ṣe láti kàn sí orílé iṣẹ́ wa tàbí ẹ̀ka ọ́fíìsì wa mọ́ nígbà yẹn. Torí náà, ó ṣe pàtàkì pé ká nífẹ̀ẹ́, ká sì máa bọ̀wọ̀ fáwọn alàgbà ìjọ wa báyìí. Ohun yòówù kó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ ká máa ronú bó ṣe tọ́. Ká má máa wo kùdìẹ̀-kudiẹ wọn. Ohun tó yẹ ká máa wò ni pé Jèhófà ti yan Kristi láti máa darí àwọn ọkùnrin olóòótọ́ yìí. Bí akoto ṣe máa ń dáàbò bo orí ọmọ ogun kan, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí tá a ní pé Jèhófà máa gbà wá là lọ́jọ́ iwájú máa ń dáàbò bò wá ká lè máa ronú bó ṣe tọ́. A mọ̀ pé kò sóhun rere kankan tí ayé yìí lè fún wa. (Fílí. 3:8) Ìrètí yìí ló ń fi wá lọ́kàn balẹ̀. w23.06 11-12 ¶11-12
Tuesday, September 9
Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo. Òpè ni.—Òwe 9:13.
Àwọn tó ń gbọ́ ohun tí “òmùgọ̀ obìnrin” yẹn ń sọ máa ní láti ṣe ìpinnu: Ṣé wọ́n máa lọ sọ́dọ̀ ẹ̀ àbí wọn ò ní lọ? Ìdí pàtàkì wà tí ò fi yẹ ká ṣèṣekúṣe. Bíbélì ní “òmùgọ̀ obìnrin” ń sọ pé: “Omi tí a jí gbé máa ń dùn.” (Òwe 9:17) Kí ni “omi tí a jí gbé”? Bíbélì sọ pé ìbálòpọ̀ tó wà láàárín tọkọtaya dà bí omi tó ń tuni lára. (Òwe 5:15-18) Ọkùnrin àti obìnrin tó ti ṣègbéyàwó sì máa ń gbádùn ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ara wọn tí wọ́n bá ṣe é lọ́nà tó tọ́. Ẹ ò rí i pé ìyẹn yàtọ̀ pátápátá sí “omi tí a jí gbé,” tó ṣeé ṣe kó jẹ́ ìbálòpọ̀ tí ò bófin mu tó ń wáyé láàárín àwọn tí ò bá ara wọn ṣègbéyàwó. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ kì í jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé wọ́n ń bára wọn lò pọ̀. Ṣe ló dà bí olè tí kì í jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ tó bá fẹ́ jí nǹkan. “Omi tí a jí gbé” máa ń dùn lẹ́nu àwọn tó ń mu ún torí wọ́n rò pé wọn ò ní jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ẹ ò rí i pé wọ́n ń tan ara wọn jẹ ni! Jèhófà ń rí gbogbo ohun tí wọ́n ń ṣe. Kò sí nǹkan tó korò tó kéèyàn pàdánù ojú rere Jèhófà, torí náà kò sí adùn kankan níbẹ̀.—1 Kọ́r. 6:9, 10. w23.06 22 ¶7-9
Wednesday, September 10
Síbẹ̀ tí kò bá ti inú mi wá, iṣẹ́ ìríjú kan ṣì wà ní ìkáwọ́ mi.—1 Kọ́r. 9:17.
Kí lo lè ṣe tó o bá rí i pé àdúrà ẹ ò tọkàn wá mọ́ tàbí pé o ò fi bẹ́ẹ̀ gbádùn iṣẹ́ òjíṣẹ́ ẹ bíi ti tẹ́lẹ̀ mọ́? Má ṣe ronú pé ẹ̀mí Jèhófà ti fi ẹ́ sílẹ̀. Torí pé aláìpé ni ẹ́, bí nǹkan ṣe ń rí lára ẹ á máa yàtọ̀ látìgbàdégbà. Tí ìtara ẹ bá ń jó rẹ̀yìn, ronú nípa àpẹẹrẹ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó máa ń gbìyànjú láti fara wé Jésù, nígbà míì kì í lè ṣe tó bó ṣe fẹ́ nínú iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run. Pọ́ọ̀lù ti pinnu pé òun máa ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ òun parí láìka bí nǹkan ṣe rí fún un lásìkò yẹn. Lọ́nà kan náà, má ṣe ìpinnu torí bí nǹkan ṣe rí lára ẹ. Pinnu pé ohun tó tọ́ lo máa ṣe, tí ò bá tiẹ̀ wù ẹ́ pé kó o ṣe bẹ́ẹ̀. Tó o bá ń ṣe nǹkan tó tọ́ nígbà gbogbo, tó bá yá, nǹkan tó dáa lá máa wù ẹ́ ṣe.—1 Kọ́r. 9:16. w24.03 11 ¶12-13
Thursday, September 11
Ẹ máa ṣe ohun tó fi hàn pé ẹ nífẹ̀ẹ́ wọn.—2 Kọ́r. 8:24.
Àwa náà lè fìfẹ́ hàn sáwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa tá a bá ń bá wọn ṣọ̀rẹ́. (2 Kọ́r. 6:11-13) Ọ̀pọ̀ lára wa ló wà nínú ìjọ tí ìwà àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa yàtọ̀ síra, tí wọ́n sì wá láti ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ìfẹ́ tá a ní sí wọn á túbọ̀ máa lágbára tá a bá ń wo ibi tí wọ́n dáa sí. Torí náà, tá a bá ń wo àwọn èèyàn bí Jèhófà ṣe ń wò wọ́n, à ń fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn nìyẹn. Ó ṣe pàtàkì pé ká nífẹ̀ẹ́ àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa nígbà ìpọ́njú ńlá. Nígbà tí ìpọ́njú ńlá bá bẹ̀rẹ̀, báwo ni Jèhófà ṣe máa dáàbò bò wá? Ẹ jẹ́ ká wo ohun tí Jèhófà ní káwọn èèyàn òun ṣe nígbà táwọn kan gbógun ja ìlú Bábílónì àtijọ́. Ó sọ pé: “Ẹ lọ, ẹ̀yin èèyàn mi, ẹ wọnú yàrá yín tó wà ní inú, kí ẹ sì ti àwọn ilẹ̀kùn yín mọ́ ara yín. Ẹ fi ara yín pa mọ́ fúngbà díẹ̀, títí ìbínú náà fi máa kọjá lọ.” (Àìsá. 26:20) Ó ṣeé ṣe káwa náà tẹ̀ lé irú ìmọ̀ràn yìí nígbà ìpọ́njú ńlá. w23.07 6-7 ¶14-16
Friday, September 12
Ìrísí ayé yìí ń yí pa dà.—1 Kọ́r. 7:31.
Jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé o máa ń fòye báni lò. Torí náà, bi ara ẹ pé: ‘Ṣé àwọn èèyàn mọ̀ mí sẹ́ni tó máa ń fòye báni lò, tí kì í rin kinkin mọ́ nǹkan, tó sì máa ń rára gba nǹkan sí? Ṣé kì í ṣe ẹni tó le koko tó sì lágídí làwọn èèyàn mọ̀ mí sí? Ṣé mo máa ń rin kinkin pé káwọn èèyàn ṣe nǹkan bí mo ṣe lérò pé ó yẹ ká ṣe é gẹ́lẹ́? Ṣé mo máa ń tẹ́tí sáwọn ẹlòmíì, tí mo sì máa ń gba èrò wọn nígbà tí mo bá rí i pé ó yẹ kí n ṣe bẹ́ẹ̀?’ Bá a bá ṣe túbọ̀ ń fòye bá àwọn èèyàn lò, bẹ́ẹ̀ làá túbọ̀ máa fara wé Jèhófà àti Jésù. Tá a bá fẹ́ fi hàn pé à ń fòye báni lò, kò yẹ ká máa rin kinkin mọ́ èrò wa tí nǹkan bá yí pa dà nígbèésí ayé wa. Irú àwọn àyípadà bẹ́ẹ̀ lè mú ká láwọn ìṣòro tá ò rò tẹ́lẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, àìsàn tá ò rò tẹ́lẹ̀ lè ṣe wá. Ohun míì ni pé lójijì, ọrọ̀ ajé lè dẹnu kọlẹ̀ tàbí kí ọ̀rọ̀ òṣèlú dá wàhálà sílẹ̀ lórílẹ̀-èdè wa, gbogbo ìyẹn sì lè mú kí nǹkan tojú súni. (Oníw. 9:11) Kódà, nǹkan lè nira tí iṣẹ́ tí ètò Ọlọ́run gbé fún wa bá yí pa dà. Àá lè fara da ipò èyíkéyìí tá a bá ń ṣe àwọn nǹkan mẹ́rin yìí, (1) gbà pé nǹkan ti yí pa dà báyìí, (2) má ṣe máa ronú nípa ohun tó ò ń ṣe tẹ́lẹ̀, ohun tó o máa ṣe sọ́rọ̀ náà ni kó o máa rò, (3) máa ronú nípa àwọn nǹkan rere tí Jèhófà ti ṣe fún ẹ àti (4) máa ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. w23.07 21-22 ¶7-8
Saturday, September 13
O ṣeyebíye gan-an.—Dán. 9:23.
Ọ̀dọ́ ni wòlíì Dáníẹ́lì nígbà táwọn ará Bábílónì mú un nígbèkùn láti Jerúsálẹ́mù lọ sílùú Bábílónì. Àmọ́, ohun táwọn ìjòyè Bábílónì rí lára Dáníẹ́lì wú wọn lórí. Wọ́n rí i pé Dáníẹ́lì ‘kò ní àbùkù kankan, ìrísí ẹ̀ dáa,’ ilé ọlá ló sì ti wá. (1 Sám. 16:7) Àwọn nǹkan tí wọ́n rí lára Dáníẹ́lì yìí ló jẹ́ káwọn ará Bábílónì dá a lẹ́kọ̀ọ́ kó lè máa ṣiṣẹ́ láàfin. (Dán. 1:3, 4, 6) Jèhófà nífẹ̀ẹ́ Dáníẹ́lì torí pé ó níwà ọmọlúàbí. Kódà, ó ṣeé ṣe kó ku díẹ̀ kí Dáníẹ́lì pé ọmọ ogún (20) ọdún tàbí kó ṣẹ̀ṣẹ̀ lé lógún ọdún nígbà tí Jèhófà dárúkọ ẹ̀ pẹ̀lú àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ ẹ̀, irú bíi Nóà àti Jóòbù tí wọ́n ti fi ọ̀pọ̀ ọdún bá Ọlọ́run rìn, tí wọ́n sì lórúkọ rere lọ́dọ̀ ẹ̀. (Jẹ́n. 5:32; 6:9, 10; Jóòbù 42:16, 17; Ìsík. 14:14) Jèhófà ò yéé nífẹ̀ẹ́ Dáníẹ́lì, kódà ó ṣe bẹ́ẹ̀ jálẹ̀ ìgbésí ayé ẹ̀.—Dán. 10:11, 19. w23.08 2 ¶1-2
Sunday, September 14
Ẹ lóye ní kíkún ohun tí ìbú àti gígùn àti gíga àti jíjìn náà jẹ́.—Éfé. 3:18.
Tó o bá fẹ́ ra ilé kan, ó dájú pé wàá fẹ́ lọ síbẹ̀ fúnra ẹ, kó o sì rí gbogbo ohun tó wà nínú ilé náà. A lè ṣe ohun tó jọ bẹ́ẹ̀ tá a bá fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Tó o bá yára kà á, “àwọn ohun àkọ́bẹ̀rẹ̀ tó wà nínú àwọn ọ̀rọ̀ ìkéde mímọ́ ti Ọlọ́run” nìkan lo máa mọ̀. (Héb. 5:12) Dípò bẹ́ẹ̀, ṣe ni kó o kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì jinlẹ̀ kó o lè mọ kúlẹ̀kúlẹ̀ ohun tó wà nínú ẹ̀, ìyẹn máa dà bíi pé o “wọnú” ilé tó o fẹ́ rà. Ọ̀nà tó dáa jù tó o lè gbà kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ni pé kó o wo bí ohun tó sọ níbì kan ṣe tan mọ́ ohun tó sọ láwọn ibòmíì. Kì í ṣe àwọn ẹ̀kọ́ òtítọ́ tó o gbà gbọ́ nìkan ló yẹ kó o mọ̀, ó tún yẹ kó o mọ ìdí tó o fi gba àwọn nǹkan náà gbọ́. Tá a bá fẹ́ lóye Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run dáadáa, àwọn nǹkan kan wà tá a gbọ́dọ̀ kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ nínú Bíbélì. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gba àwọn Kristẹni lọ́kùnrin àti lóbìnrin níyànjú pé kí wọ́n máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kí wọ́n “lè lóye ní kíkún ohun tí ìbú àti gígùn àti gíga àti jíjìn” òtítọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́. Tí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, ìgbàgbọ́ wọn á ‘ta gbòǹgbò, á sì fìdí múlẹ̀.’ (Éfé. 3:14-19) Ohun tó yẹ káwa náà ṣe nìyẹn. w23.10 18 ¶1-3
Monday, September 15
Ẹ̀yin ará, ẹ jẹ́ kí àwọn wòlíì tó sọ̀rọ̀ ní orúkọ Jèhófà jẹ́ àpẹẹrẹ fún yín nínú jíjìyà ibi àti níní sùúrù.—Jém. 5:10.
Àpẹẹrẹ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run míì tó ní sùúrù wà nínú Bíbélì. O ò ṣe kẹ́kọ̀ọ́ nípa wọn nígbà tó o bá fẹ́ dá kẹ́kọ̀ọ́? Bí àpẹẹrẹ, ìgbà tí Dáfídì ṣì kéré gan-an ni Jèhófà ti ní kí wọ́n yàn án láti jẹ́ ọba Ísírẹ́lì lọ́jọ́ iwájú, àmọ́ ọ̀pọ̀ ọdún ló fi dúró kó tó di ọba. Síméónì àti Ánà náà jọ́sìn Jèhófà tọkàntọkàn lásìkò tí wọ́n ń dúró kí Mèsáyà dé. (Lúùkù 2:25, 36-38) Bó o ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ àwọn ìtàn Bíbélì yẹn, wá ìdáhùn àwọn ìbéèrè yìí: Kí ló jẹ́ kí ẹni yìí ní sùúrù? Àǹfààní wo lẹni náà rí torí pé ó ní sùúrù? Báwo ni mo ṣe lè fara wé e? Bákan náà, tó o bá kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn tí kò ní sùúrù, wàá jàǹfààní. (1 Sám. 13:8-14) O lè bi ara ẹ pé: ‘Kí ni ò jẹ́ kí wọ́n ní sùúrù? Àwọn nǹkan burúkú wo ló ṣẹlẹ̀ sí wọn torí pé wọn ò ní sùúrù?’ w23.08 25 ¶15
Tuesday, September 16
A ti gbà gbọ́, a sì ti mọ̀ pé ìwọ ni Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.—Jòh. 6:69.
Àpọ́sítẹ́lì Pétérù jẹ́ olóòótọ́, kò sì jẹ́ kó sú òun láti máa tẹ̀ lé Jésù. Nígbà kan tí Jésù sọ ohun tí kò yé àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀, Pétérù ṣe ohun tó fi hàn pé òun jẹ́ olóòótọ́. (Jòh. 6:68) Dípò kí àwọn ọmọ ẹ̀yìn yẹn ní sùúrù, kí wọ́n sì gbọ́ àlàyé tí Jésù máa ṣe, ńṣe ni ọ̀pọ̀ lára wọn fi Jésù sílẹ̀. Àmọ́ Pétérù ò ṣe bẹ́ẹ̀. Ó mọ̀ pé Jésù ló ní “àwọn ọ̀rọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” Jésù mọ̀ pé Pétérù àtàwọn àpọ́sítélì yòókù máa sá fi òun sílẹ̀. Síbẹ̀, Jésù sọ fún Pétérù pé ó máa pa dà, ó sì máa jẹ́ olóòótọ́. (Lúùkù 22:31, 32) Jésù mọ̀ dáadáa pé “ẹ̀mí ń fẹ́, àmọ́ ẹran ara jẹ́ aláìlera.” (Máàkù 14:38) Kódà, lẹ́yìn tí Pétérù sọ pé òun ò mọ Jésù rárá, Jésù ò jẹ́ kọ́rọ̀ ẹ̀ sú òun. Lẹ́yìn tí Jésù jíǹde, ó fara han Pétérù, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ ìgbà tí Pétérù dá wà. (Máàkù 16:7; Lúùkù 24:34; 1 Kọ́r. 15:5) Ẹ ò rí i pé ìyẹn máa fún Pétérù lókun gan-an bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ti ṣàṣìṣe! w23.09 22 ¶9-10
Wednesday, September 17
Aláyọ̀ ni àwọn tí a dárí ìwà wọn tí kò bófin mu jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.—Róòmù 4:7.
Ọlọ́run máa ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn tó bá nígbàgbọ́ nínú ẹ̀ jì wọ́n. Ó máa ń dárí jì wọ́n pátápátá, kò sì ní ka ẹ̀ṣẹ̀ náà sí wọn lọ́rùn. (Sm. 32:1, 2) Jèhófà máa ń ka irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ sí aláìlẹ́bi àti olódodo torí pé wọ́n nígbàgbọ́. Jèhófà pe Ábúráhámù, Dáfídì àtàwọn ìránṣẹ́ ẹ̀ míì ní olódodo, bó tiẹ̀ jẹ́ pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni wọ́n. Àmọ́ torí pé wọ́n nígbàgbọ́, Ọlọ́run kà wọ́n sí aláìlẹ́bi pàápàá tá a bá fi wọ́n wé àwọn tí ò mọ Ọlọ́run rárá. (Éfé. 2:12) Bí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ṣe sọ nínú lẹ́tà rẹ̀, ó jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbàgbọ́ ṣe pàtàkì tá a bá fẹ́ ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Ọlọ́run. Bọ́rọ̀ Ábúráhámù àti Dáfídì ṣe rí nìyẹn. Torí pé àwa náà nígbàgbọ́, a ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà. w23.12 3 ¶6-7
Thursday, September 18
Ẹ máa rú ẹbọ ìyìn sí Ọlọ́run nípasẹ̀ rẹ̀ nígbà gbogbo, ìyẹn èso ètè wa tó ń kéde orúkọ rẹ̀ ní gbangba.—Héb. 13:15.
Gbogbo àwa Kristẹni lónìí láǹfààní láti rúbọ sí Jèhófà bá a ṣe ń lo àkókò wa, okun wa àti ohun ìní wa láti mú kí iṣẹ́ Ìjọba Ọlọ́run tẹ̀ síwájú. Torí náà, ẹ jẹ́ ká fi hàn pé a mọyì àǹfààní tá a ní láti jọ́sìn Jèhófà bá a ṣe ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe nínú iṣẹ́ ìsìn rẹ̀. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù jẹ́ ká mọ àwọn nǹkan tá a gbọ́dọ̀ máa ṣe tá a bá ń jọ́sìn Jèhófà. (Héb. 10:22-25) Àwọn nǹkan náà ni: Ká máa gbàdúrà sí Jèhófà, ká máa wàásù fáwọn èèyàn, ká máa lọ sípàdé, ká sì máa fún ara wa níṣìírí “ní pàtàkì jù lọ bí [a] ṣe ń rí i pé ọjọ́ náà ń sún mọ́lé.” Nígbà tí ìwé Ìfihàn ń parí lọ, ẹ̀ẹ̀mejì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni áńgẹ́lì Jèhófà sọ gbólóhùn yìí pé: “Ọlọ́run ni kí o jọ́sìn!” (Ìfi. 19:10; 22:9) Torí náà, ká má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ tó jinlẹ̀ tá a kọ́ nípa tẹ́ńpìlì ńlá tẹ̀mí, ká sì mọyì àǹfààní tá a ní láti máa jọ́sìn Ọlọ́run wa atóbilọ́lá! w23.10 29 ¶17-18
Friday, September 19
Ẹ jẹ́ ká túbọ̀ máa nífẹ̀ẹ́ ara wa.—1 Jòh. 4:7.
Gbogbo wa ló wù pé “ká túbọ̀ máa nífẹ̀ẹ́ ara wa.” Àmọ́, ó yẹ ká rántí ìkìlọ̀ Jésù pé “ìfẹ́ ọ̀pọ̀ jù lọ máa tutù.” (Mát. 24:12) Jésù ò sọ pé ọ̀pọ̀ lára àwọn ọmọlẹ́yìn òun ò ní fìfẹ́ hàn síra wọn mọ́. Síbẹ̀, ó yẹ ká ṣọ́ra, ká má fìwà jọ àwọn èèyàn ayé tí wọn kì í fìfẹ́ hàn sáwọn èèyàn. Torí náà, ẹ jẹ́ ká dáhùn ìbéèrè pàtàkì yìí: Kí ló máa jẹ́ ká mọ̀ bóyá ìfẹ́ tá a ní sáwọn ará ò tíì tutù? Ọ̀nà kan tá a lè fi mọ̀ bóyá a nífẹ̀ẹ́ àwọn ará dénú ni pé ká wo ohun tá a máa ń ṣe tí nǹkan bá ṣẹlẹ̀ láàárín wa. (2 Kọ́r. 8:8) Àpọ́sítélì Pétérù sọ ọ̀kan lára ohun tó yẹ ká ṣe, ó ní: “Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ara yín, torí ìfẹ́ máa ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.” (1 Pét. 4:8) Torí náà, ohun tá a bá ṣe nígbà táwọn ará bá ṣẹ̀ wá tàbí tá a bá rí kùdìẹ̀-kudiẹ wọn ló máa jẹ́ ká mọ̀ bóyá a nífẹ̀ẹ́ wọn dénú. w23.11 10 ¶12-13
Saturday, September 20
Ẹ nífẹ̀ẹ́ ara yín.—Jòh. 13:34.
Kò sí bá a ṣe lè sọ pé à ń tẹ̀ lé àṣẹ Jésù pé ká nífẹ̀ẹ́ ara wa tó bá jẹ́ pé àwọn kan là ń fìfẹ́ hàn sí nínú ìjọ, tá a sì ń pa àwọn yòókù tì. Lóòótọ́, a lè sún mọ́ àwọn kan ju àwọn míì lọ bíi ti Jésù. (Jòh. 13:23; 20:2) Àmọ́ ohun tí àpọ́sítélì Pétérù gbà wá níyànjú ni pé ká ní “ìfẹ́ ará” sí gbogbo àwọn ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin, ìyẹn irú ìfẹ́ tó máa ń wà láàárín àwọn ọmọ ìyá. (1 Pét. 2:17) Pétérù rọ̀ wá pé ká “ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ sí ara [wa] látọkàn wá.” (1 Pét. 1:22) Nínú ẹsẹ yìí, ‘ìfẹ́ tó tọkàn wá’ ni pé ká fìfẹ́ hàn sẹ́nì kan bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ṣòro fún wa láti ṣe bẹ́ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, kí la máa ṣe tí arákùnrin tàbí arábìnrin kan bá ṣẹ̀ wá tàbí tó ṣe ohun tó dùn wá gan-an? Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ohun tó máa kọ́kọ́ wá sí wa lọ́kàn ni bá a ṣe máa gbẹ̀san dípò ká fìfẹ́ hàn sí i. Àmọ́ ohun tí Jésù kọ́ Pétérù ni pé inú Ọlọ́run kì í dùn sáwọn tó bá ń gbẹ̀san. (Jòh. 18:10, 11) Pétérù sọ pé: “Ẹ má ṣe fi búburú san búburú, ẹ má sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù san ọ̀rọ̀ àbùkù. Kàkà bẹ́ẹ̀, kí ẹ máa súre.” (1 Pét. 3:9) Torí náà, ẹ jẹ́ kí ìfẹ́ tó tọkàn wá mú ká máa finúure hàn sáwọn ará, ká sì máa gba tiwọn rò. w23.09 28-29 ¶9-11
Sunday, September 21
Kí àwọn obìnrin . . . má ṣe jẹ́ aláṣejù, kí wọ́n jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun gbogbo.—1 Tím. 3:11.
Ó máa ń yà wá lẹ́nu gan-an bá a ṣe ń rí i táwọn ọmọdé ń yára dàgbà. Ńṣe làwọn àyípadà yẹn máa ń ṣàdédé wáyé bí wọ́n ṣe ń dàgbà. Àmọ́ ọ̀rọ̀ àwa Kristẹni ò rí bẹ́ẹ̀, a gbọ́dọ̀ ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe tá a bá fẹ́ kí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wa. (1 Kọ́r. 13:11; Héb. 6:1) Kíyẹn tó lè ṣeé ṣe, a gbọ́dọ̀ ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà. A tún gbọ́dọ̀ jẹ́ kí ẹ̀mí mímọ́ ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní àwọn ànímọ́ Ọlọ́run, ká kọ́ àwọn nǹkan tó máa ṣe wá láǹfààní, ká sì múra sílẹ̀ de àwọn ojúṣe tá a máa ní lọ́jọ́ iwájú. (Òwe 1:5) Nígbà tí Jèhófà dá àwa èèyàn, akọ àti abo ló dá wa. (Jẹ́n. 1:27) Ó hàn gbangba pé ìrísí ọkùnrin yàtọ̀ sí ti obìnrin, àmọ́ wọ́n tún yàtọ̀ síra láwọn ọ̀nà míì. Bí àpẹẹrẹ, Jèhófà dá ọkùnrin àti obìnrin kí wọ́n lè bójú tó àwọn ojúṣe kan, torí náà ó yẹ kí wọ́n láwọn ànímọ́ tó dáa, kí wọ́n sì kọ́ àwọn nǹkan tó máa jẹ́ kí wọ́n lè bójú tó àwọn ojúṣe náà.—Jẹ́n. 2:18. w23.12 18 ¶1-2
Monday, September 22
Ẹ máa sọ àwọn èèyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn, ẹ máa batisí wọn ní orúkọ Baba àti ti Ọmọ.—Mát. 28:19.
Ṣé Jésù fẹ́ káwọn èèyàn máa lo orúkọ Bàbá ẹ̀? Bẹ́ẹ̀ ni. Àwọn olórí ẹ̀sìn tó ka ara wọn sí olódodo sọ pé orúkọ Ọlọ́run mọ́ ju kéèyàn máa pè é lọ, àmọ́ Jésù ò jẹ́ kí àṣà tí Ìwé Mímọ́ ò fọwọ́ sí yẹn dí òun lọ́wọ́ láti bọlá fún orúkọ Bàbá òun. Ẹ jẹ́ ká wo ìgbà kan tí Jésù lé ẹ̀mí èṣù jáde lára ọkùnrin kan ní agbègbè àwọn ará Gérásà. Ẹ̀rù ba àwọn èèyàn náà gan-an, torí náà wọ́n sọ pé kí Jésù máa lọ, ó sì kúrò níbẹ̀. (Máàkù 5:16, 17) Síbẹ̀, Jésù fẹ́ káwọn èèyàn tó wà lágbègbè yẹn mọ orúkọ Jèhófà. Torí náà, ó sọ fún ọkùnrin tó wò sàn náà pé kó sọ fáwọn èèyàn pé Jèhófà ló wo òun sàn. (Máàkù 5:19) Ohun tó fẹ́ káwa náà ṣe lónìí nìyẹn, ó fẹ́ ká sọ orúkọ Bàbá ẹ̀ fún gbogbo èèyàn! (Mát. 24:14; 28:20) Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, a máa múnú Jésù Ọba wa dùn. w24.02 10 ¶10
Tuesday, September 23
O ti mú ọ̀pọ̀ nǹkan mọ́ra nítorí orúkọ mi.—Ìfi. 2:3.
Àǹfààní ńlá ló jẹ́ pé a wà lára àwọn tó ń sin Jèhófà nínú ètò ẹ̀ láwọn ọjọ́ ìkẹyìn tí nǹkan nira yìí. Bí nǹkan ṣe ń burú sí i nínú ayé, Jèhófà fi àwọn ará wa lọ́kùnrin àti lóbìnrin tá a jọ wà níṣọ̀kan kẹ́ wa. (Sm. 133:1) Ó tún ń ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní ìdílé aláyọ̀. (Éfé. 5:33–6:1) Yàtọ̀ síyẹn, ó ń fún wa ní ọgbọ́n àti òye tí àá fi máa fara da àwọn ìṣòro wa kọ́kàn wa lè balẹ̀. Torí náà, a gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ kára ká lè máa fi gbogbo ọkàn wa sin Jèhófà nìṣó. Kí nìdí? Ìdí ni pé nígbà míì, àwọn tá a jọ ń sin Jèhófà lè ṣe ohun tó dùn wá. Ó tún lè nira fún wa láti fara da àwọn àṣìṣe wa, pàápàá tó bá jẹ́ pé léraléra là ń ṣe àwọn àṣìṣe náà. Torí náà, ó ṣe pàtàkì pé ká máa sin Jèhófà nìṣó (1) táwọn ará bá ṣẹ̀ wá, (2) tí ọkọ tàbí aya wa bá já wa kulẹ̀ àti (3) tá a bá rẹ̀wẹ̀sì torí àwọn àṣìṣe wa. w24.03 14 ¶1-2
Wednesday, September 24
Níbi tí a tẹ̀ síwájú dé, ẹ jẹ́ kí a máa rìn létòlétò ní ọ̀nà kan náà.—Fílí. 3:16.
Látìgbàdégbà, wàá máa gbọ́ ìrírí àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó ti pinnu láti ṣe púpọ̀ sí i nínú iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ lè lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere Ìjọba Ọlọ́run tàbí kí wọ́n kó lọ síbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù púpọ̀ sí i. Tí ipò ẹ bá gbà ẹ́ láyè, irú àwọn nǹkan tó yẹ kíwọ náà fi ṣe àfojúsùn ẹ nìyẹn. Ìdí sì ni pé àwa èèyàn Jèhófà máa ń sapá láti ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wa. (Ìṣe 16:9) Àmọ́ ká sọ pé o ò tíì lè ṣe bẹ́ẹ̀ báyìí ńkọ́? Má ṣe rò pé o ò dáa tó àwọn tó ń ṣe bẹ́ẹ̀. Ohun tó ṣe pàtàkì jù ni pé kó o máa fi ìfaradà sá eré ìje náà nìṣó. (Mát. 10:22) Má gbàgbé pé ohun tó máa múnú Jèhófà dùn ni pé kó o máa ṣe nǹkan tágbára ẹ gbé lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ẹ̀. Ọ̀kan lára ohun tó dáa jù tó o lè ṣe láti máa tẹ̀ lé Jésù nìyẹn lẹ́yìn tó o bá ṣèrìbọmi.—Sm. 26:1. w24.03 10 ¶11
Thursday, September 25
Ó dárí gbogbo àṣemáṣe wa jì wá tinútinú.—Kól. 2:13.
Jèhófà Bàbá wa ọ̀run ṣèlérí pé òun máa dárí jì wá tá a bá ronú pìwà dà. (Sm. 86:5) Torí náà, tá a bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn torí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tá a ti dá, ó yẹ ká gbà pé òótọ́ ni Jèhófà sọ pé òun ti dárí jì wá. Máa rántí pé Jèhófà máa ń gba tiwa rò. Kì í retí pé ká ṣe ju agbára wa lọ. Ó mọyì ohunkóhun tá a bá ṣe, tó bá ṣáà ti jẹ́ pé gbogbo ohun tágbára wa gbé là ń ṣe. Bákan náà, a tún lè ronú nípa àwọn tó sin Jèhófà tọkàntọkàn nínú Bíbélì. Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù. Ọ̀pọ̀ ọdún ló fi lo ìtara lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, ó rin ìrìn ọ̀pọ̀ máìlì, ó sì dá ìjọ tó pọ̀ sílẹ̀. Síbẹ̀, nígbà tí ò lè ṣe tó ti tẹ́lẹ̀ mọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, ṣé ìyẹn wá túmọ̀ sí pé inú Jèhófà ò dùn sí i mọ́? Rárá o. Ó ń ṣe gbogbo ohun tó lè ṣe, Jèhófà sì bù kún un. (Ìṣe 28:30, 31) Lọ́nà kan náà, àwọn ìgbà míì wà tá a lè má lè ṣe tó bá a ṣe fẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Àmọ́ ohun tó ṣe pàtàkì jù lójú Jèhófà ni ìdí tá a fi ń ṣe é. w24.03 27 ¶7, 9
Friday, September 26
Ní àárọ̀ kùtù, tí ilẹ̀ ò tíì mọ́, [Jésù] dìde, ó jáde lọ síbi tó dá, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í gbàdúrà níbẹ̀.—Máàkù 1:35.
Jésù fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ nígbà tó gbàdúrà sí Jèhófà. Jálẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, gbogbo ìgbà ni Jésù máa ń gbàdúrà. Ńṣe ni Jésù máa ń wáyè gbàdúrà torí pé ọwọ́ ẹ̀ máa ń dí gan-an, ọ̀pọ̀ èèyàn sì máa ń wà lọ́dọ̀ ẹ̀. (Máàkù 6:31, 45, 46) Ó máa ń jí láàárọ̀ kùtù láti lọ dá gbàdúrà. Kódà, ìgbà kan wà tó fi gbogbo òru gbàdúrà nígbà tó fẹ́ ṣe ìpinnu pàtàkì kan. (Lúùkù 6:12, 13) Yàtọ̀ síyẹn, ní alẹ́ tó ṣáájú ikú Jésù, léraléra ló gbàdúrà sí Jèhófà bó ṣe ń ronú nípa bó ṣe máa parí èyí tó le jù lára iṣẹ́ tó wá ṣe láyé. (Mát. 26:39, 42, 44) Àpẹẹrẹ Jésù kọ́ wa pé bó ti wù kí ọwọ́ wa dí tó, ó yẹ ká máa wáyè gbàdúrà. Bíi ti Jésù, ó yẹ káwa náà ya àkókò sọ́tọ̀ láti máa gbàdúrà, ó sì lè gba pé ká tètè jí láàárọ̀ tàbí ká gbàdúrà ká tó lọ sùn lálẹ́. Tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀, àá fi hàn pé a mọyì àǹfààní tí Jèhófà fún wa láti gbàdúrà. w23.05 3 ¶4-5
Saturday, September 27
A ti tú ìfẹ́ Ọlọ́run jáde sínú ọkàn wa nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́, èyí tí a fún wa.—Róòmù 5:5.
Kíyè sí ọ̀rọ̀ náà, ‘tú jáde’ nínú ẹsẹ ojúmọ́ wa tòní. Ìwé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé a tún lè pe ọ̀rọ̀ yìí ní “dà jáde sórí wa bí omi.” Ẹ ò rí i pé ọ̀rọ̀ tá a fi ṣàpèjúwe ìfẹ́ tí Jèhófà ní sáwọn ẹni àmì òróró yìí bá a mu gan-an! Ó dá àwọn ẹni àmì òróró lójú pé ‘Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́’ àwọn. (Júùdù 1) Àpọ́sítélì Jòhánù jẹ́ ká mọ bọ́rọ̀ náà ṣe rí lára wọn, ó ní: “Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba ní sí wa tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run!” (1 Jòh. 3:1) Àmọ́, ṣé àwọn ẹni àmì òróró nìkan ni Jèhófà nífẹ̀ẹ́? Rárá o, Jèhófà ti fi hàn pé gbogbo wa lòun nífẹ̀ẹ́. Kí lohun tó ga jù lọ tí Jèhófà ṣe láti fi hàn pé òun nífẹ̀ẹ́ wa? Ìràpadà ni. Kò tíì sẹ́ni tó fi irú ìfẹ́ yìí hàn láyé àtọ̀run!—Jòh. 3:16; Róòmù 5:8. w24.01 28 ¶9-10
Sunday, September 28
Àwọn ọ̀tá mi á sá pa dà ní ọjọ́ tí mo bá ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́. Ó dá mi lójú pé: Ọlọ́run wà pẹ̀lú mi.—Sm. 56:9.
Ẹsẹ Bíbélì tó wà lókè yìí sọ nǹkan tí Dáfídì ṣe láti borí ẹ̀rù tó ń bà á. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọ̀tá ẹ̀ fẹ́ pa á, ó ronú nípa ohun tí Jèhófà máa ṣe fún òun lọ́jọ́ iwájú. Dáfídì mọ̀ pé àsìkò tó tọ́ ni Jèhófà máa gba òun sílẹ̀. Ó ṣe tán, Jèhófà ti sọ pé Dáfídì ló máa jọba lẹ́yìn Sọ́ọ̀lù. (1 Sám. 16:1, 13) Torí náà, ó dá Dáfídì lójú pé ohun tí Jèhófà ṣèlérí máa ṣẹ. Kí ni Jèhófà ṣèlérí pé òun máa ṣe fún ẹ? A mọ̀ pé kì í ṣe gbogbo ìgbà ni Jèhófà máa ń dáàbò bò wá pé kí ìṣòro má dé bá wa. Síbẹ̀, ìṣòro yòówù kó dé bá wa nísinsìnyí, Jèhófà máa mú gbogbo ẹ̀ kúrò nínú ayé tuntun. (Àìsá. 25:7-9) Ó dájú pé Ẹlẹ́dàá wa lágbára láti jí àwọn òkú dìde, láti wò wá sàn, kó sì pa gbogbo àwọn ọ̀tá wa run.—1 Jòh. 4:4. w24.01 5-6 ¶12-13
Monday, September 29
Aláyọ̀ ni ẹni tí a dárí àṣìṣe rẹ̀ jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀.—Sm. 32:1.
Máa ronú nípa ìyàsímímọ́ àti ìrìbọmi tó o ṣe. Ìdí tó o fi ya ara ẹ sí mímọ́ tó o sì ṣèrìbọmi ni pé Jèhófà ló wù ẹ́ pé kó o máa ṣègbọràn sí. Máa rántí àwọn nǹkan tó jẹ́ kó o gbà pé o ti rí òtítọ́. Ẹ̀kọ́ Bíbélì tó o kọ́ ló jẹ́ kó o mọ Jèhófà Bàbá rẹ ọ̀run, ó ti jẹ́ kó o máa bọ̀wọ̀ fún un, kó o sì nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. Ẹ̀kọ́ tó o kọ́ tún jẹ́ kó o nígbàgbọ́, kó o sì ronú pìwà dà. O ti fi àwọn ìwà tí inú Ọlọ́run ò dùn sí sílẹ̀, o sì ń ṣe ohun tó fẹ́. Ara tù ẹ́ nígbà tó o mọ̀ pé Ọlọ́run ti dárí jì ẹ́. (Sm. 32:2) O bẹ̀rẹ̀ sí í wá sípàdé ìjọ, o sì ń sọ àwọn nǹkan àgbàyanu tó o ti kọ́ fáwọn èèyàn. Ní báyìí tó o ti ya ara ẹ sí mímọ́, tó o sì ti ṣèrìbọmi, o ti bẹ̀rẹ̀ sí í rìn ní ọ̀nà ìyè, o sì ti pinnu pé o ò ní kúrò níbẹ̀. (Mát. 7:13, 14) Torí náà, a rọ̀ ẹ́ pé kó o dúró gbọn-in, kó o máa sin Jèhófà tọkàntọkàn, kó o sì máa pa àwọn àṣẹ ẹ̀ mọ́. w23.07 17 ¶14; 19 ¶19
Tuesday, September 30
Ọlọ́run jẹ́ olóòótọ́, kò ní jẹ́ kí a dán yín wò kọjá ohun tí ẹ lè mú mọ́ra, ṣùgbọ́n nínú àdánwò náà, yóò ṣe ọ̀nà àbáyọ kí ẹ lè fara dà á.—1 Kọ́r. 10:13.
Tó o bá ń ronú lórí àdúrà tó o gbà nígbà tó o ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà, wàá nígboyà láti borí ìdẹwò èyíkéyìí. Bí àpẹẹrẹ, ṣé wàá tage pẹ̀lú ẹni tí kì í ṣe ọkọ tàbí aya ẹ? Ó dájú pé o ò ní ṣe bẹ́ẹ̀! Ìdí ni pé o ti pinnu tẹ́lẹ̀ pé o ò ní ṣe bẹ́ẹ̀ láé. Tí o ò bá jẹ́ kí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ gbilẹ̀ lọ́kàn ẹ, kò ní sídìí fún ẹ láti máa wá bó o ṣe máa gbé e kúrò lọ́kàn tó bá yá. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, o ò ní “gba ọ̀nà àwọn ẹni burúkú.” (Òwe 4:14, 15) Tó o bá rántí bí Jésù ṣe pinnu pé òun máa múnú Bàbá òun dùn, kíákíá lo máa kọ irú iṣẹ́ bẹ́ẹ̀, wàá sì pinnu pé o ò ní ṣe ohunkóhun tó máa dun Jèhófà tó o ya ara ẹ sí mímọ́ fún. (Mát. 4:10; Jòh. 8:29) Òótọ́ ibẹ̀ ni pé ìṣòro àti ìdẹwò máa fún ẹ láǹfààní láti fi hàn pé o ti pinnu láti máa tẹ̀ lé Jésù. Tó o bá pinnu láti máa tẹ̀ lé Jésù, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà máa ràn ẹ́ lọ́wọ́. w24.03 9-10 ¶8-10