ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w99 2/15 ojú ìwé 3
  • Ǹjẹ́ Ò Ń Ronú Nípa Ìgbéyàwó?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Ò Ń Ronú Nípa Ìgbéyàwó?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ìjì Tó Ń Jà Yìí Ò Ní Í Gbé Ìgbéyàwó Lọ?
    Jí!—2006
  • Bí Tọkọtaya Ṣe Lè Láyọ̀ Lóde Òní
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Bí Ìgbéyàwó Bá Wà ní Bèbè Àtitúká
    Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé
  • Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Ìgbéyàwó?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
w99 2/15 ojú ìwé 3

Ǹjẹ́ Ò Ń Ronú Nípa Ìgbéyàwó?

Báa bá fi ìṣòro ìkọ̀sílẹ̀ tó gba gbogbo àgbáyé kan wé ìsẹ̀lẹ̀, Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà ni yóò jẹ́ ibi tí jàǹbá yìí yóò ti kọ́kọ́ wáyé. Lọ́dún àìpẹ́ yìí, ìgbéyàwó tó lé ní àádọ́ta ọ̀kẹ́ ni wọ́n tú ká níbẹ̀—ìpíndọ́gba ìgbéyàwó méjì-méjì ní ìṣẹ́jú kọ̀ọ̀kan. Ṣùgbọ́n, ó ṣeé ṣe kí o mọ̀ pé kì í ṣe Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà nìkan ni wàhálà ọ̀ràn ìgbéyàwó bá.

GẸ́GẸ́ bí ìwádìí kan ti sọ, láti ọdún 1970, iye ìkọ̀sílẹ̀ tó ń wáyé ní Kánádà, ilẹ̀ England àti Wales, Faransé, Gíríìsì, àti Netherlands ti lé ní ìlọ́po méjì ohun tí ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ tẹ́lẹ̀.

A kò kọminú rárá pé, ọ̀pọ̀ jù lọ tọkọtaya ń wọnú ìdè ìgbéyàwó nítorí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ ara wọn, tí wọ́n sì fẹ́ láti lo ìyókù ìgbésí ayé wọn papọ̀. Ṣùgbọ́n, ó ṣeni láàánú pé, ìdílé aláyọ̀ tí ọ̀pọ̀ ń retí kí wọ́n tó ṣègbéyàwó kì í sábà rí bẹ́ẹ̀—àlá lásán ló sábà máa ń jẹ́. Nígbà tí ọ̀pọ̀ wá mọ bó ṣe ń rí gan-an, wọ́n ní kò yẹ káwọn ti tètè ṣègbéyàwó báyẹn, àwọn mìíràn sọ pé kì í ṣe irú ẹni tó yẹ kí àwọn fẹ́ làwọn lọ fẹ́, ohun méjèèjì yìí tilẹ̀ ni àwọn mìíràn sọ.

Èé ṣe tí ọ̀pọ̀ ìgbéyàwó fi ń forí ṣánpọ́n? Òǹkọ̀wé kan lórí ìfẹ́rasọ́nà sọ pé: “Ìdí pàtàkì ni àìmúrasílẹ̀.” Obìnrin náà tún fi kún un pé: “Nínú ìbálò mi pẹ̀lú àwọn tọkọtaya tó wà nínú ìrora gógó tí ìdààmú ìgbéyàwó fà, ìmọ̀lára méjì ló máa ń dà bò mí—àánú àti ìbínú. Àánú wọn máa ń ṣe mí nítorí pé, ipò ìbátan aláyọ̀ tí wọ́n rò pé yóò wà láàárín àwọn méjèèjì kò rí bẹ́ẹ̀ mọ́. Inú máa ń bí mi nítorí wọn kò lóye bí iṣẹ́ náà ti díjú tó.”

Lóòótọ́, ọ̀pọ̀ ló ń kù gìrì wọnú ìgbéyàwó láìní òye kankan nípa bí wọ́n ṣe lè ṣàṣeyọrí. Síbẹ̀, èyí kò fi bẹ́ẹ̀ yani lẹ́nu. Olùkọ́ni kan sọ pé: “Ẹ ò mọye àwọn ọ̀dọ́ wa tó jẹ́ pé ìṣesí èkúté àti aláǹgbá ni wọ́n ń lọ kọ́ ní kọ́lẹ́ẹ̀jì, ṣùgbọ́n tí wọn ò kọ́ nípa ìṣesí àwọn ẹni méjì táà ń pè ní tọkọtaya?”

Ǹjẹ́ ò ń ronú nípa ìgbéyàwó—bóyá ò ń ronú àtiṣègbéyàwó ní ọjọ́ ọ̀la tàbí ìgbéyàwó tóo ti wà nínú rẹ̀ lò ń rò? Bóo bá ń ronú nípa ìgbéyàwó, ó yẹ kí o mọ̀ pé ipò lọ́kọláya gidi yàtọ̀ pátápátá sí èyí táà ń rí nínú sinimá, táà ń wò lórí tẹlifíṣọ̀n, àti èyí táà ń kà nínú ìwé ìtàn eléré ìfẹ́. Síbẹ̀síbẹ̀, a lè sọ pé ìgbéyàwó àwọn ẹni méjì tí wọ́n dàgbà dénú, tí wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ ara wọn dénú jẹ́ ìbùkún láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run. (Òwe 18:22; 19:14) Bó bá rí bẹ́ẹ̀, báwo ló ṣe lè dá ọ lójú pé o ti gbára dì láti kojú àwọn ohun tí ìgbéyàwó ń béèrè? Kí ni àwọn kókó tó yẹ kí o gbé yẹ̀ wò tóo bá fẹ́ yan ẹni tóo fẹ́ẹ́ fẹ́? Bó bá sì jẹ́ pé o ti ṣègbéyàwó, báwo ló ṣe lè mú kí rírí ayọ̀ pípẹ́ títí nínú ìgbéyàwó rẹ ṣeé ṣe?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́