ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w03 1/1 ojú ìwé 26
  • Obìnrin Náà Jèrè Ìfaradà Tó Ní

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Obìnrin Náà Jèrè Ìfaradà Tó Ní
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ̀yin Aya, Ẹ Ní Ọ̀wọ̀ Jíjinlẹ̀ Fún Ọkọ Yín
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Ohun Tó O Lè Ṣe Kí Ìdílé Rẹ Lè Jẹ́ Aláyọ̀
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ọlọrun Ha Gbapò Kìíní Nínú Ìdílé Rẹ Bí?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Ìmọ̀ràn Ọlọgbọ́n Fún Àwọn Tọkọtaya
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
w03 1/1 ojú ìwé 26

Obìnrin Náà Jèrè Ìfaradà Tó Ní

Ọ̀pọ̀ olódodo èèyàn ló ń fẹ́ kí àwọn tó wà nínú ìdílé òun kẹ́kọ̀ọ́ nípa ète Ọlọ́run kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ gbé ìgbésí ayé aláyọ̀. Nígbà tẹ́nì kan bá ya ara rẹ̀ sí mímọ́ fún Ọlọ́run, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìwà rere àwọn ẹlòmíràn, lọ́mọdé lágbà ló mú kí onítọ̀hún ṣe ìpinnu yẹn. Bí ọ̀ràn Jearim ṣe rí nìyẹn, ìyẹn ọ̀dọ́mọbìnrin ọlọ́dún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ní Mẹ́síkò. Òun ló fún àwọn ara ní àkọsílẹ̀ tó tẹ̀ lé e yìí ní àpéjọ àkànṣe kan táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe.

“Mo fẹ́ kẹ́ ẹ mọ̀ pé inú mi dùn ayọ̀ mi sì kún. Ẹ jẹ́ kí n sọ ìdí rẹ̀ fún yín. Àwọn òbí mi kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ ní ọdún méjìdínlógún sẹ́yìn, wọn ò tí ì bí mi nígbà yẹn. Màmá mi tẹ̀ síwájú, lẹ́yìn náà èmi àti àbúrò mi ọkùnrin tún ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú. A wá gbàdúrà pa pọ̀ pé kí Jèhófà jẹ́ kí bàbá mi náà lè wá sí ọ̀nà tó lọ sí ìyè. Ọdún méjìdínlógún ti kọjá, òní yìí sì jẹ́ ọjọ́ àkànṣe fún wa. Bàbá mi ṣe ìrìbọmi lónìí. Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà pé kò mú òpin náà dé ṣáájú ọjọ́ pàtàkì tá a ti ń retí tipẹ́ yìí. Jèhófà o ṣé o!”

Bí ọdún ti ń gorí ọdún, ó dájú pé ìdílé ọ̀dọ́mọbìnrin yìí ti fi ìlànà tó wà nínú ìmọ̀ràn onímìísí inú 1 Pétérù 3:1, 2 sọ́kàn, èyí tó sọ pé: “Ẹ̀yin aya, ẹ wà ní ìtẹríba fún àwọn ọkọ tiyín, kí ó lè jẹ́ pé, bí ẹnikẹ́ni kò bá ṣègbọràn sí ọ̀rọ̀ náà, kí a lè jèrè wọn láìsọ ọ̀rọ̀ kan nípasẹ̀ ìwà àwọn aya wọn, nítorí fífi tí wọ́n fi ojú rí ìwà mímọ́ yín pa pọ̀ pẹ̀lú ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀.” Ó sì dájú pé Jearim tó jẹ́ ọ̀dọ́ náà á ti fi àwọn ọ̀rọ̀ inú Diutarónómì 5:16 sílò, èyí tó sọ pé: “Bọlá fún baba rẹ àti ìyá rẹ, gẹ́gẹ́ bí Jèhófà Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún ọ gan-an.” Ó dájú pé fífi irú ìlànà bẹ́ẹ̀ sílò àti fífi sùúrù dúró de àkókò Jèhófà mú ìbùkún yabuga wá fún Jearim àti ìdílé rẹ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́