ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w07 4/1 ojú ìwé 3
  • Àwọn Èèyàn Ń Wá Ìdáhùn Tó Tọ̀nà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Èèyàn Ń Wá Ìdáhùn Tó Tọ̀nà
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ọ̀pọ̀ Èèyàn Ń Wá Ìmọ̀ràn Tó Wúlò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Iṣẹ́ Tí Jèhófà Rán Sí Àwọn Èèyàn Ayé Ọjọ́un Ṣì Wà Fún Wa Lónìí
    Máa Fi Ọjọ́ Jèhófà Sọ́kàn
  • Àwọn Ìmọ̀ràn Tó Wúlò Gan-an!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Ẹ̀kọ́ Òtítọ́ Tínú Ọlọ́run Dùn Sí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
w07 4/1 ojú ìwé 3

Àwọn Èèyàn Ń Wá Ìdáhùn Tó Tọ̀nà

Kí ni mo lè ṣe tí mi ò ní fọwọ́ ara mi fa àìsàn?

Kí ni mo lè ṣe tí ayọ̀ á fi túbọ̀ wà nínú ìdílé mi?

Kí ni mo lè ṣe tí iṣẹ́ ò fi ní bọ́ lọ́wọ́ mi?

ǸJẸ́ o tiẹ̀ ti béèrè èyíkéyìí lára àwọn ìbéèrè yìí rí? Ǹjẹ́ o rí ìdáhùn tó ràn ẹ́ lọ́wọ́ gan-an? Nǹkan bí ẹgbẹ̀rún méjì onírúurú ìwé tó ń fúnni nímọ̀ràn lórí àwọn ọ̀ràn yìí àtàwọn ọ̀ràn mìíràn tó ṣe pàtàkì làwọn èèyàn ń ṣe jáde lọ́dọọdún. Nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì nìkan ṣoṣo, ọdọọdún làwọn òǹkàwé ń ná nǹkan bí àádọ́jọ [150] mílíọ̀nù owó dọ́là sórí àwọn ìwé tó ń fúnni nímọ̀ràn nípa ohun téèyàn lè ṣe sáwọn ìṣòro ìgbésí ayé. Lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, nǹkan bí ẹgbẹ̀ta [600] mílíọ̀nù dọ́là ló ń wọlé lọ́dún lórí àwọn ìwé afúnni-nímọ̀ràn. Ó dájú pé ìwọ nìkan kọ́ ló ń wá ìmọ̀ràn tó dára láti mọ ọ̀nà tó o máa gbà bójú tó àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nígbèésí ayé rẹ lójoojúmọ́.

Nígbà tí òǹṣèwé kan ń sọ̀rọ̀ lórí àwọn ìmọ̀ràn tó wà nínú àwọn ìwé tó pọ̀ jaburata yìí, ó ní: “Ohun tó wà nínú àwọn ìwé tí wọ́n ti ṣe jáde tẹ́lẹ̀ ni ọ̀pọ̀ ìwé tuntun wulẹ̀ ń tún sọ.” Ká sòótọ́, èyí tó pọ̀ jù lára ìmọ̀ràn inú àwọn ìwé yìí ló jẹ́ pé ńṣe ni wọ́n kàn ń ṣàtúnsọ ọgbọ́n tó wà lákọsílẹ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìwé tọ́jọ́ wọn pẹ́ jù lọ láyé. Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ má síbì kan lágbàáyé téèyàn ò ti lè rí ìwé tá a ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí. Wọ́n ti túmọ̀ rẹ̀ lódindi tàbí lápá kan sáwọn èdè tó tó ẹgbẹ̀rún méjì ó lé irínwó [2,400]. Lápapọ̀, iye tí wọ́n ti tẹ̀ jáde kárí ayé ń lọ sí bílíọ̀nù márùn-ún. Bíbélì ni ìwé tá à ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí.

Bíbélì fúnra rẹ̀ sọ pé: “Gbogbo Ìwé Mímọ́ ni Ọlọ́run mí sí, ó sì ṣàǹfààní fún kíkọ́ni, fún fífi ìbáwí tọ́ni sọ́nà, fún mímú àwọn nǹkan tọ́, fún bíbániwí nínú òdodo.” (2 Tímótì 3:16) Àmọ́ o, Bíbélì kì í ṣe ìwé tó kàn ń fúnni nímọ̀ràn lásán. Olórí ohun tó wà fún ni pé káwọn èèyàn lè mọ ohun tí Ọlọ́run fẹ́ ṣe fún aráyé. Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ nǹkan ni Bíbélì sọ nípa ọ̀nà tá a lè gbà kojú àwọn ìṣòro táwa èèyàn sábà máa ń ní. Bíbélì tún jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn tó bá tẹ̀ lé ìtọ́sọ́nà tó wà nínú Bíbélì á jàǹfààní. (Aísáyà 48:17, 18) Láìka ẹ̀yà téèyàn ti wá tàbí àṣà ìṣẹ̀dálẹ̀ ẹni sí, tàbí yálà èèyàn jẹ́ ọ̀mọ̀wé tàbí púrúǹtù, téèyàn bá ń fi ìmọ̀ràn inú Bíbélì sílò, ó máa ń ṣeni láǹfààní gan-an. O ò ṣe ka àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí kó o sì wá fúnra rẹ pinnu bóyá ohun tí Bíbélì sọ wúlò lórí àwọn nǹkan bí ọ̀rọ̀ ìlera, ìdílé àti iṣẹ́?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́