ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 12/15 ojú ìwé 4-5
  • Jèhófà Máa Ń Bù Kún Àwọn Tó Ní Ẹ̀mí Ìmúratán

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jèhófà Máa Ń Bù Kún Àwọn Tó Ní Ẹ̀mí Ìmúratán
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Iṣẹ́ Náà Pọ̀”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Mọrírì Ìwà Ọ̀làwọ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àṣẹ́kùsílẹ̀ Wọn Dí Àìnító Kan
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Bá A Ṣe Lè Ṣèrànwọ́ Fún Àwọn Èèyàn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 12/15 ojú ìwé 4-5

Jèhófà Máa Ń Bù Kún Àwọn Tó Ní Ẹ̀mí Ìmúratán

ẸLẸ́DÀÁ wa ti fi ẹ̀bùn iyebíye kan dá àwa èèyàn lọ́lá, ìyẹn ni bó ṣe dá wa lọ́nà tá a fi lè yan ohun tó wù wá. Bákan náà, ó máa ń bù kún àwọn tó bá lo òmìnira yìí láti fi mú kí ìjọsìn tòótọ́ gbòòrò, tí wọ́n ń sa gbogbo ipá wọn kí wọ́n lè sọ orúkọ rẹ̀ di mímọ́ tí wọ́n sì kọ́wọ́ ti ohun tó jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run. Jèhófà ò fẹ́ ká máa ṣègbọràn sí òun torí pé ó di dandan fún wa tàbí torí ìbẹ̀rù. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó máa ń mọyì rẹ̀ gan-⁠an tó bá jẹ́ pé ojúlówó ìfẹ́ àti ìmọrírì àtọkànwá ló mú ká máa jọ́sìn òun.

Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wà ní aginjù Sínáì, Jèhófà sọ fún wọn pé kí wọ́n kọ́ ibi ìjọsìn. Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ gba ọrẹ fún Jèhófà. Kí gbogbo ọlọ́kàn ìmúratán mú un wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ Jèhófà.” (Ẹ́kís. 35:5) Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lè mú ohunkóhun tí wọ́n bá ní wá. Ohun yòówù tí ì báà jẹ́, yálà ó pọ̀ tàbí ó kéré, wọ́n máa lò ó láti fi ṣe ohun tí Jèhófà sọ pé kí wọ́n ṣe. Kí wá làwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe?

Bíbélì sọ pé, “olúkúlùkù ẹni tí ọkàn-àyà rẹ̀ sún un ṣiṣẹ́” àti “olúkúlùkù ẹni tí ẹ̀mí rẹ̀ ru ú sókè” ṣe ọrẹ àfínnúfíndọ̀ṣe, ‘ọkàn ìmúratán’ ni wọ́n fi ṣe é. Àtọkùnrin àtobìnrin ni wọ́n mú nǹkan wá fún iṣẹ́ Jèhófà, lára ohun tí wọ́n mú wá ni: àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àsomáṣọ, àwọn yẹtí, àwọn òrùka, wúrà, fàdákà, bàbà, fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, irun àgùntàn tí a fi àwọ̀ àlùkò àdàpọ̀-mọ́-pupa pa láró, òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò ti kòkòrò kókọ́sì, aṣọ ọ̀gbọ̀ àtàtà, irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a pa láró pupa, awọ séálì, igi bọn-ọ̀n-ní, àwọn òkúta iyebíye, básámù àti òróró. Nígbẹ̀yìngbẹ́yín, “ohun èlò náà tó fún gbogbo iṣẹ́ tí [wọ́n fẹ́] ṣe, ó tó, ó sì ṣẹ́ kù.”​—Ẹ́kís. 35:​21-24, 27-29; 36:7.

Kì í ṣe ohun tí wọ́n mú wá ló mú inú Jèhófà dùn, bí kò ṣe ẹ̀mí ìmúratán tí wọ́n fi ń kọ́wọ́ ti ìjọsìn mímọ́. Àwọn èèyàn yìí tún yọ̀ǹda àkókò àti okun wọn. Bíbélì sọ pé: “Gbogbo àwọn obìnrin . . . fi ọwọ́ wọn rànwú.” Kódà, “gbogbo obìnrin tí ọkàn-àyà wọn sún wọn ṣiṣẹ́ . . . ran irun ewúrẹ́.” Yàtọ̀ síyẹn, Jèhófà fún Bẹ́sálẹ́lì ní ‘ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ gbogbo onírúurú ọgbọ́n iṣẹ́ ọnà.’ Ọlọ́run fi gbogbo ọgbọ́n ọnà tí Bẹ́sálẹ́lì àti Òhólíábù nílò kún inú wọn kí wọ́n lè ṣe gbogbo iṣẹ́ tí ó gbé fún wọn.​—Ẹ́kís. 35:​25, 26, 30-35.

Nígbà tí Jèhófà sọ pé káwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣètìlẹ́yìn, ó dá a lójú pé “gbogbo ọlọ́kàn ìmúratán” máa kọ́wọ́ ti ìjọsìn tòótọ́. Àwọn tó fi ẹ̀mí ìmúratán ṣètìlẹ́yìn ni Jèhófà bù kún jìngbìnnì, ó dáàbò bò wọ́n ó sì mú kí wọ́n láyọ̀. Èyí fi hàn pé Jèhófà máa ń bù kún ẹ̀mí ìmúratán tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá fi hàn, ó sì máa ń fún wọn ní ìmọ̀ àti gbogbo ohun tí wọ́n nílò láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ. (Sm. 34:9) Bó o ṣe ń sin Jèhófà tọkàntọkàn, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà máa bù kún ẹ̀mí ìmúratán tí o bá fi hàn.

Ọ̀nà Táwọn Kan Ń gbà Ṣètọrẹ Fún Iṣẹ́ Kárí Ayé

Bó ṣe rí nígbà ayé àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, ọ̀pọ̀ èèyàn máa ń “ya ohun kan sọ́tọ̀,” tàbí kí wọ́n ya iye owó kan sọ́tọ̀, kí wọ́n sì fi owó náà sínú àpótí ìjọ tá a kọ “Ọrẹ fún Iṣẹ́ Kárí Ayé” sí. (1 Kọ́r. 16:2) Oṣooṣù làwọn ìjọ máa ń fi owó yìí ránṣẹ́ sí ẹ̀ka ọ́fíìsì àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà lórílẹ̀-èdè wọn. O sì tún lè fi ọrẹ ránṣẹ́ ní tààràtà sí ẹ̀ka ọ́fíìsì àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó ń bójú tó orílẹ̀-èdè rẹ. Tó o bá fẹ́ mọ orúkọ àjọ tó ń bójú tó iṣẹ́ wa lábẹ́ òfin, jọ̀wọ́ kàn sí ẹ̀ka ọ́fí ìsì tó ń bójú tó iṣẹ́ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà lórílẹ̀-èdè rẹ. O lè rí àdírẹ́sì ẹ̀ka ọ́fí ìsì náà lórí ìkànnì www.jw.org/yo. Lára àwọn ọrẹ tó o lè fi ránṣẹ́ sí wa ní tààràtà rèé:

Ẹ̀BÙN

  • O lè fi ọrẹ ránṣẹ́ látinú àkáǹtì rẹ lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì tàbí kó o lo káàdì tí owó wà lórí rẹ̀ tàbí káàdì tí wọ́n fi ń rajà láwìn láti fi ọrẹ ránṣẹ́. Ní àwọn ẹ̀ka ọ́fíìsì kan, o lè fi ọrẹ ránṣẹ́ látorí Ìkànnì jw.org tàbí ìkànnì míì tí ẹ̀ka ọ́fíìsì bá fọwọ́ sí.

  • O lè fi owó, ohun ọ̀ṣọ́ tó ṣeyebíye tàbí dúkìá mìíràn ṣètọrẹ. Kọ lẹ́tà kó o sì fi ránṣẹ́ pẹ̀lú owó tàbí ọrẹ náà láti fi hàn pé ẹ̀bùn ló jẹ́.

ỌRẸ TÓ ṢEÉ GBÀ PA DÀ

  • O lè fi owó síkàáwọ́ àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò pé kí wọ́n máa lò ó. Àmọ́, àjọ náà máa dá owó náà pa dà tó o bá béèrè fún un.

  • Kọ lẹ́tà láti fi hàn pé ńṣe lo fi owó náà síkàáwọ́ àjọ náà títí dìgbà tí wàá fẹ́ láti gbà á pa dà.

ỌRẸ TÉÈYÀN WÉWÈÉ

Yàtọ̀ sí pé ká dìídì fi owó tàbí dúkìá mìíràn ṣètọrẹ, àwọn ọ̀nà mìíràn tún wà tá a lè gbà ṣètọrẹ tó máa ṣàǹfààní fún iṣẹ́ Ìjọba Ọlọ́run kárí ayé. Ọ̀nà yòówù kó o fẹ́ láti gbà ṣètọrẹ, jọ̀wọ́ kọ́kọ́ kàn sí ẹ̀ka ọ́fíìsì tó ń bójú tó iṣẹ́ wa lórílẹ̀-èdè rẹ, kí wọ́n lè jẹ́ kó o mọ ọ̀nà tó bófin mu tó o lè gbà ṣe é. Ohun tí òfin sọ nípa ọrẹ máa ń yàtọ̀ síra, ó ṣe pàtàkì pé kó o fi ọ̀rọ̀ lọ amòfin tó mọ̀ nípa ẹ̀ dáadáa kó o tó yan ọ̀nà tó o máa gbà ṣètọrẹ. Díẹ̀ lára àwọn ọ̀nà tó o lè gbà ṣètọrẹ rèé:

Owó Ìbánigbófò: A lè kọ orúkọ àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò gẹ́gẹ́ bí ẹni tí yóò gba owó ìbánigbófò ẹ̀mí tàbí owó ìfẹ̀yìntì ẹni lẹ́nu iṣẹ́.

Àkáǹtì Owó ní Báńkì: A lè fi àkáǹtì owó tá a ní sí báńkì, tàbí owó tá a fi pa mọ́ sí báńkì fún àkókò pàtó kan, tàbí àkáǹtì owó ìfẹ̀yìntì ẹni lẹ́nu iṣẹ́, síkàáwọ́ àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò pé kí àjọ náà máa lò ó tàbí ká ṣètò pé kí wọ́n san owó náà fún àjọ náà lẹ́yìn ikú ẹni gẹ́gẹ́ bí ìlànà báńkì ti sọ.

Ìpín Ìdókòwò, Ẹ̀tọ́ Orí Owó Ìdókòwò àti Ti Ètò Ẹ̀yáwó: A lè fi ẹ̀tọ́ ìpín ìdókòwò, ẹ̀tọ́ orí owó ìdókòwò àti ti ẹ̀yáwó ta àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò lọ́rẹ. A sì lè tọwọ́ bọ ìwé àdéhùn, pé kí ẹ̀tọ́ náà di ti àjọ náà lẹ́yìn ikú ẹni.

Ilẹ̀ àti Ilé: A lè fi ilẹ̀ tó ṣeé tà tọrẹ fún àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò, yálà nípa fífi ṣe ẹ̀bùn, tàbí tó bá jẹ́ ilẹ̀ tí ilé wà lórí rẹ̀ téèyàn ṣì ń gbé inú rẹ̀, olùtọrẹ náà lè fi tọrẹ àmọ́ kó sọ pé òun á ṣì máa gbé inú rẹ̀ ní gbogbo ìgbà tóun bá ṣì wà láàyè.

Ìwé Ìhágún àti Ohun Ìní Téèyàn Fi Síkàáwọ́ Onígbọ̀wọ́: A lè fi dúkìá tàbí owó sílẹ̀ bí ogún fún àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò nípasẹ̀ ìwé ìhágún tá a ṣe lábẹ́ òfin, tàbí ká ṣe ìwé pé àjọ náà ni ẹni tí yóò ni ohun ìní tá a fi síkàáwọ́ onígbọ̀wọ́.

Gbólóhùn náà, “ọrẹ téèyàn wéwèé” fi hàn pé ẹni tó fẹ́ ṣètọrẹ gbọ́dọ̀ ronú dáadáa kó tó ṣe irú ìtọrẹ bẹ́ẹ̀.

Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i nípa ọ̀rọ̀ yìí, kó o kàn sí ẹ̀ka ọ́fí ìsì àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó ń bójú tó orílẹ̀-èdè rẹ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́