ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 4/1 ojú ìwé 3-4
  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Ka Bíbélì?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Fún Gbogbo Èèyàn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Ẹ̀kọ́ Òtítọ́ Tínú Ọlọ́run Dùn Sí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Kí Ni Bíbélì?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 4/1 ojú ìwé 3-4
Ọkùnrin kan ń ṣàyẹ̀wò Bíbélì níbi ìkówèésí rẹ̀

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ṢÉ WÀÁ FẸ́ KẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ?

Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

  • Kí nìdí tá a fi wà láyé?

  • Kí nìdí tá a fi ń jìyà tá a sì ń kú?

  • Kí ló máa ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ ọ̀la?

  • Ṣé Ọlọ́run bìkítà nípa mi?

Ǹjẹ́ o ti bi ara rẹ ní irú àwọn ìbéèrè yìí rí? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, mọ̀ pé kì í ṣe ìwọ nìkan lo ní irú èrò bẹ́ẹ̀. Kárí ayé làwọn èèyàn ti ń wá ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè tó ṣe pàtàkì nígbèésí ayé. Ǹjẹ́ o lè rí ìdáhùn?

Ọ̀pọ̀ èèyàn máa dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni!” Kí nìdí? Ìdí ni pé wọ́n ti rí àwọn ìdáhùn tó tẹ́ wọn lọ́rùn nínú Bíbélì. Ṣé wàá fẹ́ mọ ohun tí Bíbélì sọ? Tó o bá fẹ́ bẹ́ẹ̀, ẹ̀kọ́ Bíbélì tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń kọ́ àwọn èèyàn lọ́fẹ̀ẹ́ máa ṣe ẹ́ láǹfààní.a

Tó bá kan pé ká kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, àwọn kan máa ń sọ pé: “Mi ò kì í ráyè.” “Ó ti le jù.” “Mi ò fẹ́ràn kí n máa ṣàdéhùn.” Àmọ́, èrò àwọn míì yàtọ̀ síyẹn. Wọ́n gbà láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Jẹ́ ká wo àwọn àpẹẹrẹ mélòó kan:

  • “Mo ti lọ sí ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì àti ti Pùròtẹ́sítáǹtì, mo lọ sí tẹ́ńpìlì àwọn ẹlẹ́sìn Sikh, mo ṣe ẹ̀sìn Búdà, mo sì lọ kẹ́kọ̀ọ́ ìsìn ní yunifásítì. Àmọ́, mi ò rí ìdáhùn sí ọ̀pọ̀ ìbéèrè tó ń jẹ mí lọ́kàn. Lọ́jọ́ kan, Ẹlẹ́rìí Jèhófà kan wá sí ilé mi. Bó ṣe fi Bíbélì dáhùn àwọn ìbéèrè mi wú mi lórí. Èyí sì mú kí n gbà láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.”—Gill, ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì.

  • “Mo ní ọ̀pọ̀ ìbéèrè nípa ìgbésí ayé, àmọ́ pásítọ̀ ṣọ́ọ̀ṣì mi kò fún mi ní ìdáhùn tó tẹ́ mi lọ́rùn. Àmọ́, Ẹlẹ́rìí Jèhófà kan fi Bíbélì nìkan dáhùn àwọn ìbéèrè mi. Nígbà tó béèrè bóyá máa fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ sí i, tayọ̀tayọ̀ ni mo gbà.”—Koffi, Benin.

  • “Mo fẹ́ mọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sáwọn tó ti kú. Mo gbà pé àwọn òkú lè ṣe àwọn èèyàn ní jàǹbá, àmọ́ ó wù mí láti mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa rẹ̀. Torí náà, mo bẹ̀rẹ̀ sí í kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́dọ̀ ọ̀rẹ́ mi tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà.”—José, Brazil.

  • “Mo ka Bíbélì, àmọ́ ohun tí mo kà kò yé mi. Lọ́jọ́ kan, àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì ṣàlàyé àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì mélòó kan fún mi. Èyí mú kó wù mí láti mọ̀ sí i.”—Dennize, Mẹ́síkò.

  • “Mo máa ń ronú pé bóyá ni Ọlọ́run bìkítà nípa mi. Torí náà, mo gbàdúrà sí Ọlọ́run tí Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ní ọjọ́ kejì, àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà wá sílé mi, mo sì gbà láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.”—Anju, Nepal.

Àwọn ìrírí yìí rán wa létí ohun tí Jésù sọ pé: “Aláyọ̀ ni àwọn tí àìní wọn nípa ti ẹ̀mí ń jẹ lọ́kàn.” (Mátíù 5:3) Ká sòótọ́, ó máa ń wù wá láti mọ Ọlọ́run. Ọlọ́run nìkan sì lẹni tó lè mú ká mọ òun nípasẹ̀ Bíbélì, Ọ̀rọ̀ rẹ̀.

Báwo la ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? Ọ̀nà wo ni ẹ̀kọ́ yìí máa gbà ṣe ẹ́ láǹfààní? A máa rí ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè yìí nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí.

a Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà ni orúkọ Ọlọ́run.

Ìsọfúnni Nípa Bíbélì

Bíbélì tí wọ́n ṣí sílẹ̀
  • ORÚKỌ: Látinú ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà bi·bliʹa, tó túmọ̀ sí “àwọn ìwé kéékèèké”

  • OHUN TÓ WÀ NÍNÚ RẸ̀: Ìwé 39 ní èdè Hébérù (pẹ̀lú ojú ìwé mélòó kan ní èdè Árámáíkì) àti ìwé 27 ní èdè Gíríìkì

  • BÍ WỌ́N ṢE KỌ Ọ́: Nǹkan bíi 40 èèyàn ló kọ ọ́, ó sì gbà ju 1,600 ọdún lọ, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún 1513 Ṣ.S.K. sí nǹkan bí ọdún 98 S.K.b

  • IYE ÈDÈ: Ó ti wà lápá kan tàbí lódindi ní èdè tó lé ní 2,500

  • ÌPÍNKIRI: Wọ́n ti tẹ nǹkan bíi bílíọ̀nù mẹ́rin Bíbélì, èyí mú kó jẹ́ ìwé tí wọ́n tíì pín kiri jù lọ kárí ayé

b Ìkékúrú yìí Ṣ.S.K. túmọ̀ sí “Ṣáájú Sànmánì Kristẹni.” S.K. sì túmọ̀ sí “Sànmánì Kristẹni.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́