ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 5/1 ojú ìwé 8
  • Ọ̀pọ̀ Èèyàn Máa La Òpin Já Ìwọ Náà Lè Làájá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọ̀pọ̀ Èèyàn Máa La Òpin Já Ìwọ Náà Lè Làájá
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ǹjẹ́ o Ní “Ẹ̀mí Ìdúródeni”?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • “Máa Fi Ọjọ́ Jèhófà Sọ́kàn Dáadáa”
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Ìwọ Ha Wà ní Sẹpẹ́ De Ọjọ́ Jèhófà Bí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Ohun Tí Ọjọ́ Jèhófà Máa Ṣí Payá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 5/1 ojú ìwé 8
Ẹlẹ́rìí Jèhófà kan ń ṣàlàyé Bíbélì fún obìnrin kan

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ǸJẸ́ ÒPIN TI SÚN MỌ́LÉ

Ọ̀pọ̀ Èèyàn Máa La Òpin Já Ìwọ Náà Lè Làájá

Bíbélì sọ pé òpin tó ń bọ̀ máa mú ìparun wá, ó sọ pé: “Ìpọ́njú ńlá yóò wà, irúfẹ́ èyí tí kò tíì ṣẹlẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé títí di ìsinsìnyí . . . láìjẹ́ pé a ké ọjọ́ wọnnì kúrú, kò sí ẹran ara kankan tí à bá gbà là.” (Mátíù 24:21, 22) Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run jẹ́ ká mọ̀ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni yóò làájá, ó sọ pé: “Ayé ń kọjá lọ . . . , ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò dúró títí láé.”—1 Jòhánù 2:17.

Bó o bá fẹ́ la ayé tó ń kọjá lọ yìí já, tó o sì fẹ́ wà láàyè títí láé, kí ló yẹ kó o ṣe? Àbí, ṣé ohun tó kàn ni pé kó o máa kó àwọn nǹkan ìní jọ pelemọ tàbí kó o máa gbara dì lójú méjèèjì? Rárá. Bíbélì sọ ohun tó fẹ́ ká fi sí ipò àkọ́kọ́. Ó ní: “Níwọ̀n bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò ti di yíyọ́ báyìí, irú ènìyàn wo ni ó yẹ kí ẹ jẹ́ nínú ìṣe ìwà mímọ́ àti àwọn iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run, ní dídúró de wíwàníhìn-ín ọjọ́ Jèhófà.” (2 Pétérù 3:10-12) Àyíká ọ̀rọ̀ yìí fi hàn pé àwọn alákòóso inú ayé oníwà ìbàjẹ́ yìí àti gbogbo àwọn tó fara mọ́ ìṣàkóso èèyàn dípò Ọlọ́run ló dúró fún “gbogbo nǹkan wọ̀nyí” tí yóò di yíyọ́. Ká sòótọ́, tó bá jẹ́ àwọn nǹkan ìní tara là ń tọ́jú pamọ́, ìyẹn kò ní lè dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ ìparun tó ń bọ̀.

Tá a bá fẹ́ là á já, a ní láti fi gbogbo ọkàn wa sin Jèhófà Ọlọ́run, ká sì kẹ́kọ̀ọ́ ká lè mọ àwọn ìwà àti ìṣe tó máa dùn mọ́ ọn nínú. (Sefanáyà 2:3) Tá a bá fẹ́ fi hàn pé a ‘fi ọjọ́ Jèhófà sọ́kàn pẹ́kípẹ́kí,’ a ní láti yẹra fún ohun tí ọ̀pọ̀ èèyàn gbà gbọ́ ká sì fọkàn sí àwọn àmì tó fi hàn pé àkókò tí kò lẹ́gbẹ́ là ń gbé. Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa fi ohun tí Bíbélì sọ hàn ẹ́, kó o lè mọ bí wà á ṣe la òpin tó ń bọ̀ já.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́