ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 6/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Ẹ Kọ́ Àwọn Ọmọ Yín Láti Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Ẹ̀yin Òbí, Ẹ Ran Àwọn Ọmọ Yín Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
  • Báwo Ni Ìdílé Rẹ Ṣe Lè Jẹ́ Aláyọ̀?—Apá Kejì
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 6/1 ojú ìwé 16

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Báwo lo ṣe lè jẹ́ òbí rere?

Bàbá kan àti ọmọ rẹ̀ ń wo lámilámi

Ǹjẹ́ o máa ń kọ́ àwọn ọmọ rẹ kí wọ́n lè nífẹ̀ẹ́ ọlọ́run?

Àwọn ọmọ máa ń ṣe dáadáa nínú ilé tí bàbá àti ìyá bá ti fẹ́ràn ara wọn, tí wọ́n sì ń bọ̀wọ̀ fún ara wọn. (Kólósè 3:14, 19) Jèhófà Ọlọ́run máa ń  gbóríyìn fún Ọmọ rẹ̀. Bákan náà, àwọn òbí tó mọṣẹ́ wọn níṣẹ́ máa ń nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì máa ń gbóríyìn fún wọn.—Ka Mátíù 3:17.

Baba wa ọ̀run máa ń tẹ́tí sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì máa ń kíyè sí bí nǹkan ṣe ń rí lára wọn. Ó máa dáa kí àwọn òbí kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ Jèhófà, kí wọ́n sì máa fetí sí àwọn ọmọ wọn. (Jákọ́bù 1:19) Ẹ máa ro bí ọ̀rọ̀ ṣe ń rí lára àwọn ọmọ yín. Bí àwọn ọmọ bá tiẹ̀ sọ ohun kan tó kù díẹ̀ káàtó pàápàá, ẹ má ṣe kó ọ̀rọ̀ wọn dànù.—Ka Númérì 11:11, 15.

Báwo lo ṣe lè tọ́ àwọn ọmọ rẹ yanjú?

Ojúṣe ẹ̀yin òbí ni láti máa fún àwọn ọmọ yín ní ìlànà tí wọ́n á máa tẹ̀ lé. (Éfésù 6:1) Ó máa dáa kẹ́ ẹ tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jèhófà. Ọ̀nà kan tí Jèhófà gbà fi hàn pé òun nífẹ̀ẹ́ àwa ọmọ rẹ̀ ni pé, ó fún wa ní àwọn ìlànà tó ṣe kedere. Ó sì sọ ohun tó máa jẹ́ àbájáde rẹ̀ tá a bá ṣe àìgbọ́ràn. (Jẹ́nẹ́sísì 3:3) Ọlọ́run kì í fipá mú wa láti tẹ̀ lé òfin rẹ̀, kàkà bẹ́ẹ̀ ńṣe ló jẹ́ ká mọ àǹfààní tá a máa rí tí a bá ń ṣe ohun tó tọ́.—Ka Aísáyà 48:18, 19.

Pinnu pé wà á tọ́ àwọn ọmọ rẹ kí wọ́n lè nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run. Ìyẹn á jẹ́ kí wọ́n lè máa ṣe ohun tó tọ́, kódà bí wọn kò bá sí lọ́dọ̀ rẹ. Bí Ọlọ́run ṣe máa ń fi àpẹẹrẹ rẹ̀ kọ́ wa lẹ́kọ̀ọ́, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ kó o máa fi ìwà rere rẹ kọ́ àwọn ọmọ rẹ lẹ́kọ̀ọ́, kí wọ́n lè nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run.—Ka Diutarónómì 6:5-7; Éfésù 4:32; 5:1.

Fún ìsọfúnni síwájú sí i, wo orí 14 nínú ìwé Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

Ó tún wà lórí ìkànnì www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́