ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp18 No. 1 ojú ìwé 12-13
  • 3 Ó Ń Jẹ́ Ká Fara Da Ìṣòro

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 3 Ó Ń Jẹ́ Ká Fara Da Ìṣòro
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2018
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÀÌSÀN TÓ LE GAN-AN
  • Ẹ̀DÙN ỌKÀN
  • Bí Àdúrà Ṣe Lè Ràn Ẹ́ Lọ́wọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2021
  • Àǹfààní Tó O Máa Rí Nínú Àdúrà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Bí Àwọn Kan Ṣe Rí Ìdáhùn Gbà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Sọ fún Wọn Pé O Nífẹ̀ẹ́ Wọn
    Ìrírí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2018
wp18 No. 1 ojú ìwé 12-13
Obìnrin kan ń sunkún lẹ́gbẹ̀ẹ́ sàréè; obìnrin kan tó jókòó sórí kẹ̀kẹ́ arọ ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Bíbélì

3 Ó Ń Jẹ́ Ká Fara Da Ìṣòro

Àwọn ìṣòro kan wà tá ò lè yẹra fún, kò sì sí ohun tá a lè ṣe láti yanjú wọn báyìí. Bí àpẹẹrẹ, tí ẹni tó o nífẹ̀ẹ́ gan-an bá kú tàbí tó o bá ń ṣàìsàn tó le gan-an, o lè má rí ohunkóhun ṣe sí i ju pé kó o wá bí wàá ṣe máa fara dà á lọ. Ṣé Bíbélì lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ nírú àkókò tó le yìí?

ÀÌSÀN TÓ LE GAN-AN

Obìnrin kan tó ń jẹ́ Rose sọ pé: “Mo ní àrùn inú ẹ̀jẹ̀ tó ń jẹ́ kí ara máa ro mí gan-an ní gbogbo ìgbà. Ọ̀rọ̀ ayé mi sú mi pátápátá.” Ohun tó ká a lára jù ni pé nígbà míì, ìṣòro yìí kì í jẹ́ kó lè gbádùn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àti àwọn nǹkan míì tó jẹ mọ́ ìjọsìn tó ń ṣe. Àmọ́ ọ̀rọ̀ Jésù tó wà ní Mátíù 19:26 ràn án lọ́wọ́ gan-an, Jésù sọ pé: “Lọ́dọ̀ Ọlọ́run ohun gbogbo ṣeé ṣe.” Rose wá rí i pé ọ̀nà míì tún wà tí òun lè máa gbà kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Torí pé ara tó máa ń ro ó kì í jẹ́ kó rọrùn fún un rárá láti ka Bíbélì nígbà míì, ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ́tí sí Bíbélì àtàwọn ìtẹ̀jáde míì tá a gba ohùn wọn sílẹ̀.a Ó sọ pé: “Mi ò bá má ní àjọṣe tó dán mọ́rán pẹ̀lú Ọlọ́run ká ní mi ò ṣe ohun tí mo ṣe yẹn láti máa kẹ́kọ̀ọ́.”

Nígbà tí ìbànújẹ́ dorí Rose kodò torí pé kò lè ṣe àwọn nǹkan tó máa ń ṣe tẹ́lẹ̀, ọ̀rọ̀ tó wà ní 2 Kọ́ríńtì 8:12 tù ú nínú, ẹsẹ Bíbélì náà sọ pé: “Bí ìmúratán bá kọ́kọ́ wà, ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà ní pàtàkì ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí ènìyàn ní, kì í ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí ènìyàn kò ní.” Ọ̀rọ̀ ìtùnú yìí jẹ́ kí Rose rántí pé inú Ọlọ́run ń dùn sí ìsapá rẹ̀ torí pé gbogbo ohun tí agbára rẹ̀ gbé ló ń ṣe.

Ẹ̀DÙN ỌKÀN

Delphine tá a sọ̀rọ̀ ẹ̀ nínú àpilẹ̀kọ tó ṣáájú èyí sọ pé: “Lẹ́yìn tí ọmọ mi obìnrin tó jẹ́ ọmọ ọdún méjìdínlógún [18] kú, ìbànújẹ́ mi pọ̀ débi pé mi ò mọ̀ pé màá ṣì wà láàyè títí di báyìí. Nǹkan ò lè dà bíi ti tẹ́lẹ̀ mọ́.” Àmọ́, ọ̀rọ̀ tó wà ní Sáàmù 94:19 tù ú nínú gan-an, ẹni tó kọ sáàmù yẹn sọ fún Ọlọ́run pé: “Nígbà tí ìrònú tí ń gbé mi lọ́kàn sókè di púpọ̀ nínú mi, ìtùnú tìrẹ ni ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣìkẹ́ ọkàn mi.” Delphine wá sọ pé: “Mo gbàdúrà sí Jèhófà pé kó jẹ́ kí n rí ohun tí mo lè ṣe táá jẹ́ kí ara tù mí.”

Ni Delphine bá jẹ́ kí ọwọ́ rẹ̀ dí lẹ́nu iṣẹ́ ìyọ̀ǹda ara ẹni. Nígbà tó yá, ó fi ara rẹ̀ wé pẹ́ńsù tó kán, àmọ́ tó ṣì wúlò téèyàn bá tún un gbẹ́. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀dùn ọkàn tó ní jẹ́ kó dà bí ẹni pé ó kán, síbẹ̀ ó gbà pé òun ṣì lè ran àwọn ẹlòmíì lọ́wọ́. Delphine sọ pé: “Bí mo ṣe ń fi àwọn ìlànà Bíbélì kọ́ àwọn èèyàn, tí mo sì ń jẹ́ kí wọ́n mọ bí wọ́n ṣe lè ronú lórí ohun tí Ìwé Mímọ́ sọ kó lè tù wọ́n nínú, mo wá rí i pé ńṣe ni Jèhófà ń fi ìyẹn tu èmi náà nínú, tó sì ń mú ẹ̀dùn ọkàn mi fúyẹ́.” Delphine kọ orúkọ àwọn tí Bíbélì sọ pé wọ́n ní ẹ̀dùn ọkàn tó le gan-an bíi tiẹ̀ sínú ìwé kan. Ó wá sọ pé òun kíyè sí i pé “gbogbo wọn pátá ni kò fi àdúrà ṣeré.” Ó tún sọ pé òun ti rí i pé “téèyàn bá ń ka Bíbélì léèyàn tó lè rí ohun tó máa ràn án lọ́wọ́ láti fara da ẹ̀dùn ọkàn.”

Ohun míì tó wá yé Delphine bó ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ni pé ó yẹ kí òun máa ronú nípa ọjọ́ iwájú, kì í ṣe ohun tó ti ṣẹlẹ̀ kọjá. Ọ̀rọ̀ tó ń fúnni ní ìrètí tó wà nínú Ìṣe 24:15 tù ú nínú, ẹsẹ náà kà pé: “Àjíǹde àwọn olódodo àti àwọn aláìṣòdodo yóò wà.” Báwo ló ṣe dá Delphine lójú tó pé Jèhófà máa jí ọmọbìnrin rẹ̀ dìde? Òun fúnra rẹ̀ sọ pé: “Mò ń fojú inú wo bí ọmọbìnrin mi ṣe máa jíǹde lọ́jọ́ iwájú. Ó dá mi lójú pé Jèhófà ti mú ọjọ́ tá a tún máa ríra. Rekete ni mò ń rí èmi àti ẹ̀ nínú ọgbà wa, tí mo sì ń kẹ́ ẹ bí mo ṣe kẹ́ ẹ lọ́jọ́ tí mo bí i.”

a Ọ̀pọ̀ àwọn ìtẹ̀jáde tá a gba ohùn wọn sílẹ̀ yìí ló wà lórí ìkànnì jw.org/yo.

Bíbélì lè tù ẹ́ nínú kódà ní àwọn ìgbà tí wàhálà bá bá ẹ

Báwo Ni Ọlọ́run Ṣe ń ràn Wá Lọ́wọ́?

Bíbélì dáhùn ìbéèrè yìí lọ́nà tó ṣe kedere. Ó ní: “Jèhófà ń bẹ nítòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, nítòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é ní òótọ́. Ìfẹ́-ọkàn àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ni òun yóò mú ṣẹ, igbe wọn fún ìrànlọ́wọ́ ni òun yóò sì gbọ́, yóò sì gbà wọ́n là.” (Sáàmù 145:​18, 19) Ṣé ìyẹn ò múnú rẹ dùn? Báwo wá ni Ọlọ́run ṣe máa dáhùn àdúrà àwọn tó ń wá ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ lójú méjèèjì?

ỌLỌ́RUN MÁA Ń FÚN WA NÍ OKUN ÀTI AGBÁRA:

Ìṣòro lè mú káyé sú èèyàn, ó lè tánni lókun, kó mú kéèyàn máa ro èròkérò, ó sì lè mú kéèyàn jìnnà sí Ọlọ́run. (Òwe 24:10) Àmọ́ Jèhófà “ń fi agbára fún ẹni tí ó ti rẹ̀; ó sì ń mú kí ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ agbára ńlá pọ̀ gidigidi fún ẹni tí kò ní okun alágbára.” (Aísáyà 40:29) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, tó láwọn ìṣòro tó le gan-an sọ pé: “Mo ní okun fún ohun gbogbo nípasẹ̀ agbára ìtóye ẹni tí ń fi agbára fún mi.” (Fílípì 4:13) Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ló fún Pọ́ọ̀lù lókun àti agbára. Ìwọ náà lè bẹ Ọlọ́run pé kó fún ẹ ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀.​—Lúùkù 11:13.

ỌLỌ́RUN MÁA Ń FÚN WA NÍ ỌGBỌ́N:

Tó o bá nílò ìrànlọ́wọ́ láti lóye ìmọ̀ràn Bíbélì kó o sì fi wọ́n sílò ńkọ́? Jákọ́bù tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù sọ pé: “Bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣaláìní ọgbọ́n, kí ó máa bá a nìṣó ní bíbéèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí òun a máa fi fún gbogbo ènìyàn pẹ̀lú ìwà ọ̀làwọ́ àti láìsí gíganni; a ó sì fi í fún un.” (Jákọ́bù 1:5) O lè ṣe ohun tó bá àdúrà tí ò ń gbà mu tó o bá ń ka Bíbélì tó o sì ń fi ohun tó o kọ́ ṣèwà hù. (Jákọ́bù 1:​23-25) Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, ó máa jẹ́ kó o rí bí àwọn ìmọ̀ràn Bíbélì ṣe wúlò tó.

ỌLỌ́RUN MÁA Ń FÚN WA NÍ ÀLÀÁFÍÀ:

Tó o bá tiẹ̀ ní ẹ̀dùn ọkàn tó lágbára pàápàá, Jèhófà lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ kára lè tù ẹ́. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé: “Ẹ má ṣe máa ṣàníyàn nípa ohunkóhun, ṣùgbọ́n nínú ohun gbogbo nípasẹ̀ àdúrà àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ pa pọ̀ pẹ̀lú ìdúpẹ́ kí ẹ máa sọ àwọn ohun tí ẹ ń tọrọ di mímọ̀ fún Ọlọ́run; àlàáfíà Ọlọ́run tí ó ta gbogbo ìrònú yọ yóò sì máa ṣọ́ ọkàn-àyà yín àti agbára èrò orí yín nípasẹ̀ Kristi Jésù.” (Fílípì 4:​6, 7) Ìwọ náà lè bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ ní àlàáfíà?

Àmọ́ tí ìṣòro rẹ kò bá lọ bọ̀rọ̀ ńkọ́? Má ṣe ronú pé Ọlọ́run ti pa ẹ́ tì. Kódà táwọn ìṣòro náà ò bá lọ bọ̀rọ̀, Ọlọ́run ṣì lè fún ẹ ní ìgboyà àti agbára láti fara dà á. (1 Kọ́ríńtì 10:13) Bíbélì sì tún ṣèlérí pé àkókò kan ń bọ̀ tí gbogbo ìṣòro wa máa yanjú pátápátá!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́